الصافات

تفسير سورة الصافات

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالصَّافَّاتِ صَفًّا﴾

(Allāhu búra pẹ̀lú) àwọn mọlāika olùtò-lọ́wọ̀ọ̀wọ́ tààrà;

﴿فَالزَّاجِرَاتِ زَجْرًا﴾

àti àwọn mọlāika t’ó ń wọ́ ẹ̀ṣújò kiri tààrà;

﴿فَالتَّالِيَاتِ ذِكْرًا﴾

àti àwọn mọlāika òǹké-tírà ìrántí.

﴿إِنَّ إِلَٰهَكُمْ لَوَاحِدٌ﴾

Dájúdájú Ọlọ́hun yín, Ọ̀kan ṣoṣo ni;

﴿رَبُّ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ وَمَا بَيْنَهُمَا وَرَبُّ الْمَشَارِقِ﴾

Olúwa àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ àti ohunkóhun tí ń bẹ láààrin àwọn méjèèjì. Òun sì ni Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn.

﴿إِنَّا زَيَّنَّا السَّمَاءَ الدُّنْيَا بِزِينَةٍ الْكَوَاكِبِ﴾

Dájúdájú Àwa fi àwọn ìràwọ̀ ṣe sánmọ̀ ilé ayé ní ọ̀ṣọ́

﴿وَحِفْظًا مِنْ كُلِّ شَيْطَانٍ مَارِدٍ﴾

àti ìṣọ́ níbi (aburú) gbogbo èṣù olóríkunkun.

﴿لَا يَسَّمَّعُونَ إِلَى الْمَلَإِ الْأَعْلَىٰ وَيُقْذَفُونَ مِنْ كُلِّ جَانِبٍ﴾

(Àwọn èṣù) kò sì níí lè tẹ́tí sí ìjọ (mọlāika t’ó wà ní) àyè gíga jùlọ (nínú sánmọ̀). (Àwọn mọlāika) yó sì máa ku (àwọn èṣù) lókò (ẹ̀ta ìràwọ̀) ní gbogbo agbègbè (sánmọ̀).

﴿دُحُورًا ۖ وَلَهُمْ عَذَابٌ وَاصِبٌ﴾

Wọ́n ń lé wọn dànù. Ìyà àìlópin sì wà fún wọn.

﴿إِلَّا مَنْ خَطِفَ الْخَطْفَةَ فَأَتْبَعَهُ شِهَابٌ ثَاقِبٌ﴾

(Wọn kò níí gbọ́ ọ̀rọ̀ ní kíkún) àyàfi ẹni tí ó bá rí ọ̀rọ̀ àjígbọ́ gbé, nígbà náà (ni mọlāika) yó sì fi ẹ̀ta ìràwọ̀ iná t’ó máa jó o tẹ̀lé e.

﴿فَاسْتَفْتِهِمْ أَهُمْ أَشَدُّ خَلْقًا أَمْ مَنْ خَلَقْنَا ۚ إِنَّا خَلَقْنَاهُمْ مِنْ طِينٍ لَازِبٍ﴾

Bi wọ́n léèrè wò pé ṣé àwọn ni ìṣẹ̀dá wọn lágbára jùlọ ni tàbí àwọn (ènìyàn) tí A dá? Dájúdájú Àwa dá wọn láti ara erùpẹ̀ t’ó lẹ̀ mọ́ra wọn.

﴿بَلْ عَجِبْتَ وَيَسْخَرُونَ﴾

Rárá (kò jọra wọn); ìwọ ṣèèmọ̀ (nípa al-Ƙur’ān), àwọn sì ń ṣe yẹ̀yẹ́.

﴿وَإِذَا ذُكِّرُوا لَا يَذْكُرُونَ﴾

Àti pé nígbà tí wọ́n bá ṣe ìrántí fún wọn, wọn kò níí lo ìrántí.

﴿وَإِذَا رَأَوْا آيَةً يَسْتَسْخِرُونَ﴾

Nígbà tí wọ́n bá tún rí àmì kan, wọn yóò máa ṣe yẹ̀yẹ́.

﴿وَقَالُوا إِنْ هَٰذَا إِلَّا سِحْرٌ مُبِينٌ﴾

Wọ́n sì wí pé: "Èyí kò jẹ́ kiní kan bí kò ṣe idán pọ́nńbélé.

﴿أَإِذَا مِتْنَا وَكُنَّا تُرَابًا وَعِظَامًا أَإِنَّا لَمَبْعُوثُونَ﴾

Ṣé nígbà tí a bá kú tán, tí a ti di erùpẹ̀ àti egungun, ṣé dájúdájú Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?

﴿أَوَآبَاؤُنَا الْأَوَّلُونَ﴾

Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"

﴿قُلْ نَعَمْ وَأَنْتُمْ دَاخِرُونَ﴾

Sọ pé: "Bẹ́ẹ̀ ni. Ẹ̀yin yó sì di ẹni yẹpẹrẹ."

﴿فَإِنَّمَا هِيَ زَجْرَةٌ وَاحِدَةٌ فَإِذَا هُمْ يَنْظُرُونَ﴾

Nítorí náà, igbe ẹyọ kan mà ni. Nígbà náà ni wọn yóò máa wò sùn.

﴿وَقَالُوا يَا وَيْلَنَا هَٰذَا يَوْمُ الدِّينِ﴾

Wọ́n á wí pé: "Ègbé wa! Èyí ni Ọjọ́ ẹ̀san."

﴿هَٰذَا يَوْمُ الْفَصْلِ الَّذِي كُنْتُمْ بِهِ تُكَذِّبُونَ﴾

Èyí ni ọjọ́ Ìdájọ́ èyí tí ẹ̀ ń pè nírọ́.

﴿۞ احْشُرُوا الَّذِينَ ظَلَمُوا وَأَزْوَاجَهُمْ وَمَا كَانُوا يَعْبُدُونَ﴾

Ẹ kó àwọn t’ó ṣàbòsí jọ, àwọn ìyàwó wọn àti ohun tí wọ́n ń jọ́sìn fún

﴿مِنْ دُونِ اللَّهِ فَاهْدُوهُمْ إِلَىٰ صِرَاطِ الْجَحِيمِ﴾

lẹ́yìn Allāhu. Kí ẹ sì júwe wọn sí ojú ọ̀nà iná Jẹhīm.

﴿وَقِفُوهُمْ ۖ إِنَّهُمْ مَسْئُولُونَ﴾

Ẹ dá wọn dúró ná, dájúdájú wọ́n máa bi wọ́n léèrè ìbéèrè.

﴿مَا لَكُمْ لَا تَنَاصَرُونَ﴾

Kí ni kò jẹ́ kí ẹ ranra yín lọ́wọ́?

﴿بَلْ هُمُ الْيَوْمَ مُسْتَسْلِمُونَ﴾

Rárá, wọ́n ti juwọ́ jusẹ̀ sílẹ̀ ní òní ni.

﴿وَأَقْبَلَ بَعْضُهُمْ عَلَىٰ بَعْضٍ يَتَسَاءَلُونَ﴾

Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, tí wọn yóò máa bira wọn léèrè ìbéèrè.

﴿قَالُوا إِنَّكُمْ كُنْتُمْ تَأْتُونَنَا عَنِ الْيَمِينِ﴾

(Àwọn ènìyàn) wí pé: "Dájúdájú ẹ̀yin l’ẹ̀ ń gba ọ̀tún wọlé sí wa lára (láti ṣì wá lọ́nà)."

﴿قَالُوا بَلْ لَمْ تَكُونُوا مُؤْمِنِينَ﴾

(Àwọn àlùjànnú) wí pé: "Rárá o (àwa kọ́), ẹ̀yin ni ẹ kò jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَمَا كَانَ لَنَا عَلَيْكُمْ مِنْ سُلْطَانٍ ۖ بَلْ كُنْتُمْ قَوْمًا طَاغِينَ﴾

Àti pé àwa kò ní agbára kan lórí yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin jẹ́ ìjọ olùtayọ-ẹnu àlà.

﴿فَحَقَّ عَلَيْنَا قَوْلُ رَبِّنَا ۖ إِنَّا لَذَائِقُونَ﴾

Ọ̀rọ̀ Olúwa wa sì kò lé wa lórí pé dájúdájú àwa yóò tọ́ Iná wò.

﴿فَأَغْوَيْنَاكُمْ إِنَّا كُنَّا غَاوِينَ﴾

Nítorí náà, a ṣì yín lọ́nà. Dájúdájú àwa náà sì jẹ́ olùṣìnà."

﴿فَإِنَّهُمْ يَوْمَئِذٍ فِي الْعَذَابِ مُشْتَرِكُونَ﴾

Dájúdájú ní ọjọ́ yẹn, akẹgbẹ́ ni wọ́n nínú Ìyà.

﴿إِنَّا كَذَٰلِكَ نَفْعَلُ بِالْمُجْرِمِينَ﴾

Dájúdájú báyẹn ni Àwa yóò ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

﴿إِنَّهُمْ كَانُوا إِذَا قِيلَ لَهُمْ لَا إِلَٰهَ إِلَّا اللَّهُ يَسْتَكْبِرُونَ﴾

Dájúdájú nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé "Kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Allāhu.", wọn yóò máa ṣègbéraga.

﴿وَيَقُولُونَ أَئِنَّا لَتَارِكُو آلِهَتِنَا لِشَاعِرٍ مَجْنُونٍ﴾

Wọ́n sì ń wí pé: "Ṣé a máa fi àwọn òrìṣà wa sílẹ̀ nítorí eléwì wèrè kan?"

﴿بَلْ جَاءَ بِالْحَقِّ وَصَدَّقَ الْمُرْسَلِينَ﴾

Kò rí bẹ́ẹ̀. Ó mú òdodo wá ni. Ó sì ń jẹ́rìí sí òdodo àwọn Òjíṣẹ́ náà.

﴿إِنَّكُمْ لَذَائِقُو الْعَذَابِ الْأَلِيمِ﴾

Dájúdájú ẹ máa tọ́ ìyà ẹlẹ́ta-eléro wò.

﴿وَمَا تُجْزَوْنَ إِلَّا مَا كُنْتُمْ تَعْمَلُونَ﴾

A ò níí san yín ní ẹ̀san kan àfi ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.

﴿إِلَّا عِبَادَ اللَّهِ الْمُخْلَصِينَ﴾

Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.

﴿أُولَٰئِكَ لَهُمْ رِزْقٌ مَعْلُومٌ﴾

Ti àwọn wọ̀nyẹn sì ni arísìkí tí wọ́n ti mọ̀;

﴿فَوَاكِهُ ۖ وَهُمْ مُكْرَمُونَ﴾

àwọn èso. Àwọn sì ni alápọ̀n-ọ́nlé

﴿فِي جَنَّاتِ النَّعِيمِ﴾

nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.

﴿عَلَىٰ سُرُرٍ مُتَقَابِلِينَ﴾

Lórí àwọn ìtẹ́ ni wọn yóò ti kọjú síra wọn.

﴿يُطَافُ عَلَيْهِمْ بِكَأْسٍ مِنْ مَعِينٍ﴾

Wọn yóò máa gbé ife ọtí mímọ́ káà kiri ọ̀dọ̀ wọn.

﴿بَيْضَاءَ لَذَّةٍ لِلشَّارِبِينَ﴾

Funfun ni (ọtí náà). Ó ń dùn lẹ́nu àwọn t’ó máa mu ún.

﴿لَا فِيهَا غَوْلٌ وَلَا هُمْ عَنْهَا يُنْزَفُونَ﴾

Kò sí ìpalára kan fún wọn nínú rẹ̀, wọn kò sì níí hunrírà lórí rẹ̀.

﴿وَعِنْدَهُمْ قَاصِرَاتُ الطَّرْفِ عِينٌ﴾

Àwọn obìnrin tí kì í wo ẹlòmíìràn, àwọn ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ yó sì wà lọ́dọ̀ wọn.

﴿كَأَنَّهُنَّ بَيْضٌ مَكْنُونٌ﴾

Wọ́n dà bí tinú ẹyin.

﴿فَأَقْبَلَ بَعْضُهُمْ عَلَىٰ بَعْضٍ يَتَسَاءَلُونَ﴾

Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, tí wọn yóò máa bira wọn léèrè ìbéèrè.

﴿قَالَ قَائِلٌ مِنْهُمْ إِنِّي كَانَ لِي قَرِينٌ﴾

Òǹsọ̀rọ̀ kan nínú wọn yóò sọ pé: "Dájúdájú èmi ní ọ̀rẹ́ kan

﴿يَقُولُ أَإِنَّكَ لَمِنَ الْمُصَدِّقِينَ﴾

tí ó ń wí pé, “Ṣé dájúdájú ìwọ wà nínú àwọn onígbàgbọ́ nínú Ọjọ́ Àjíǹde?

﴿أَإِذَا مِتْنَا وَكُنَّا تُرَابًا وَعِظَامًا أَإِنَّا لَمَدِينُونَ﴾

Ṣé nígbà tí a bá kú tán, tí a ti di erùpẹ̀ àti egungun, ṣé dájúdájú Wọn yóò san wá ní ẹ̀san ni?”

﴿قَالَ هَلْ أَنْتُمْ مُطَّلِعُونَ﴾

Ó sọ pé: "Ṣé ẹ̀yin yóò yọjú wo (ẹni náà tí kò gbàgbọ́ nínú Ọjọ́ àjíǹde)?"

﴿فَاطَّلَعَ فَرَآهُ فِي سَوَاءِ الْجَحِيمِ﴾

Ó yọjú wò ó. Ó sì rí i láààrin gbùngbùn nínú iná Jẹhīm.

﴿قَالَ تَاللَّهِ إِنْ كِدْتَ لَتُرْدِينِ﴾

Ó (sì) sọ pé: "Mó fi Allāhu búra, ìwọ fẹ́ẹ̀ kó ìparun bá mi tán.

﴿وَلَوْلَا نِعْمَةُ رَبِّي لَكُنْتُ مِنَ الْمُحْضَرِينَ﴾

Àti pé tí kì í bá ṣe ìdẹ̀ra Olúwa mi ni, èmi náà ìbá wà nínú ẹni tí wọ́n máa mú wá sínú Iná.

﴿أَفَمَا نَحْنُ بِمَيِّتِينَ﴾

Àwa kò sá níí kú mọ́ báyìí?

﴿إِلَّا مَوْتَتَنَا الْأُولَىٰ وَمَا نَحْنُ بِمُعَذَّبِينَ﴾

Àfi ikú wa àkọ́kọ́. Wọn kò sì níí jẹ àwa níyà.

﴿إِنَّ هَٰذَا لَهُوَ الْفَوْزُ الْعَظِيمُ﴾

Dájúdájú èyí, òhun ni èrèǹjẹ ńlá."

﴿لِمِثْلِ هَٰذَا فَلْيَعْمَلِ الْعَامِلُونَ﴾

Nítorí irú èyí, kí àwọn olùṣẹ̀sìn máa ṣẹ̀sìn lọ.

﴿أَذَٰلِكَ خَيْرٌ نُزُلًا أَمْ شَجَرَةُ الزَّقُّومِ﴾

Ǹjẹ́ ìyẹn l’ó lóore jùlọ ní ibùdésí ni tàbí igi zaƙūm (igi ẹlẹ́gùn-ún)?

﴿إِنَّا جَعَلْنَاهَا فِتْنَةً لِلظَّالِمِينَ﴾

Dájúdájú Àwa ṣe é ní àdánwò fún àwọn alábòsí.

﴿إِنَّهَا شَجَرَةٌ تَخْرُجُ فِي أَصْلِ الْجَحِيمِ﴾

Dájúdájú òhun ni igi kan tí ó máa hù jáde láti ìdí iná Jẹhīm.

﴿طَلْعُهَا كَأَنَّهُ رُءُوسُ الشَّيَاطِينِ﴾

Èso rẹ̀ dà bí orí àwọn èṣù.

﴿فَإِنَّهُمْ لَآكِلُونَ مِنْهَا فَمَالِئُونَ مِنْهَا الْبُطُونَ﴾

Dájúdájú wọn yóò máa jẹ nínú rẹ̀. Nítorí náà, wọn yóò fi kún inú wọn bámúbámú.

﴿ثُمَّ إِنَّ لَهُمْ عَلَيْهَا لَشَوْبًا مِنْ حَمِيمٍ﴾

Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò mu n̄ǹkan mímu àwọyúnwẹ̀jẹ̀ gbígbóná lé e lórí.

﴿ثُمَّ إِنَّ مَرْجِعَهُمْ لَإِلَى الْجَحِيمِ﴾

Lẹ́yìn náà, dájúdájú ibùpadàsí wọn ni iná Jẹhīm.

﴿إِنَّهُمْ أَلْفَوْا آبَاءَهُمْ ضَالِّينَ﴾

Dájúdájú wọ́n bá àwọn bàbá wọn ní olùṣìnà.

﴿فَهُمْ عَلَىٰ آثَارِهِمْ يُهْرَعُونَ﴾

Àwọn náà sì ń yára tẹ̀lé orípa wọn.

﴿وَلَقَدْ ضَلَّ قَبْلَهُمْ أَكْثَرُ الْأَوَّلِينَ﴾

Dájúdájú ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn ẹni àkọ́kọ́ ti ṣìnà ṣíwájú wọn.

﴿وَلَقَدْ أَرْسَلْنَا فِيهِمْ مُنْذِرِينَ﴾

Dájúdájú A ti rán àwọn olùkìlọ̀ sí wọn.

﴿فَانْظُرْ كَيْفَ كَانَ عَاقِبَةُ الْمُنْذَرِينَ﴾

Nítorí náà, wo bí àtubọ̀tán àwọn ẹni-akìlọ̀-fún ti rí.

﴿إِلَّا عِبَادَ اللَّهِ الْمُخْلَصِينَ﴾

Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.

﴿وَلَقَدْ نَادَانَا نُوحٌ فَلَنِعْمَ الْمُجِيبُونَ﴾

Dájúdájú (Ànábì) Nūh pè Wá. A sì dára ní olùjẹ́pè.

﴿وَنَجَّيْنَاهُ وَأَهْلَهُ مِنَ الْكَرْبِ الْعَظِيمِ﴾

A gba òun àti àwọn ará ilé rẹ̀ là kúrò nínú ìbànújẹ́ ńlá.

﴿وَجَعَلْنَا ذُرِّيَّتَهُ هُمُ الْبَاقِينَ﴾

A dá àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ sí lẹ́yìn rẹ̀.

﴿وَتَرَكْنَا عَلَيْهِ فِي الْآخِرِينَ﴾

A sì fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.

﴿سَلَامٌ عَلَىٰ نُوحٍ فِي الْعَالَمِينَ﴾

Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) Nūh láààrin gbogbo ẹ̀dá.

﴿إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿إِنَّهُ مِنْ عِبَادِنَا الْمُؤْمِنِينَ﴾

Dájúdájú òun wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿ثُمَّ أَغْرَقْنَا الْآخَرِينَ﴾

Lẹ́yìn náà, A tẹ àwọn yòókù rì sínú agbami.

﴿۞ وَإِنَّ مِنْ شِيعَتِهِ لَإِبْرَاهِيمَ﴾

Dájúdájú (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm wà nínú ìjọ (tí ó tẹ̀lé ìlànà) rẹ̀.

﴿إِذْ جَاءَ رَبَّهُ بِقَلْبٍ سَلِيمٍ﴾

(Ẹ rántí) nígbà tí òun náà dojú kọ Olúwa rẹ̀ pẹ̀lú ọkàn mímọ́.

﴿إِذْ قَالَ لِأَبِيهِ وَقَوْمِهِ مَاذَا تَعْبُدُونَ﴾

(Rántí) nígbà tí ó sọ fún bàbá rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: "Kí ni ẹ̀ ń jọ́sìn fún?

﴿أَئِفْكًا آلِهَةً دُونَ اللَّهِ تُرِيدُونَ﴾

Ṣé ẹ̀ ń gbèrò láti sọ irọ́ di ọlọ́hun lẹ́yìn Allāhu?

﴿فَمَا ظَنُّكُمْ بِرَبِّ الْعَالَمِينَ﴾

Kí sì ni èrò ọkàn yín sí Olúwa gbogbo ẹ̀dá?”

﴿فَنَظَرَ نَظْرَةً فِي النُّجُومِ﴾

Ó ṣíjú wo àwọn ìràwọ̀ gan-an.

﴿فَقَالَ إِنِّي سَقِيمٌ﴾

Ó sì sọ pé: "Dájúdájú ó rẹ̀ mí."

﴿فَتَوَلَّوْا عَنْهُ مُدْبِرِينَ﴾

Nítorí náà, wọ́n pa á tì, wọ́n sì lọ.

﴿فَرَاغَ إِلَىٰ آلِهَتِهِمْ فَقَالَ أَلَا تَأْكُلُونَ﴾

Nígbà náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn òrìṣà wọn. Ó sì sọ pé: "Ṣé ẹ ò níí jẹun ni?

﴿مَا لَكُمْ لَا تَنْطِقُونَ﴾

Kí ni ó ṣe yín tí ẹ ò sọ̀rọ̀?"

﴿فَرَاغَ عَلَيْهِمْ ضَرْبًا بِالْيَمِينِ﴾

Nígbà náà, ó dojú lílù kọ wọ́n pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún (ó sì rún wọn wómúwómú).

﴿فَأَقْبَلُوا إِلَيْهِ يَزِفُّونَ﴾

(Àwọn abọ̀rìṣà) sáré wá dojú kọ ọ́.

﴿قَالَ أَتَعْبُدُونَ مَا تَنْحِتُونَ﴾

Ó sọ pé: "Ṣé ẹ óò máa jọ́sìn fún n̄ǹkan tí ẹ gbẹ́ kalẹ̀ lére ni?

﴿وَاللَّهُ خَلَقَكُمْ وَمَا تَعْمَلُونَ﴾

Allāhu l’Ó sì dá ẹ̀yin àti n̄ǹkan tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́."

﴿قَالُوا ابْنُوا لَهُ بُنْيَانًا فَأَلْقُوهُ فِي الْجَحِيمِ﴾

Wọ́n wí pé: "Ẹ mọ ilé kan fún un, kí ẹ sì jù ú sínú iná."

﴿فَأَرَادُوا بِهِ كَيْدًا فَجَعَلْنَاهُمُ الْأَسْفَلِينَ﴾

Wọ́n gbèrò ète sí i. A sì sọ wọ́n di ẹni yẹpẹrẹ.

﴿وَقَالَ إِنِّي ذَاهِبٌ إِلَىٰ رَبِّي سَيَهْدِينِ﴾

Ó sọ pé: "Dájúdájú mo máa lọ sí (ìlú tí) Olúwa mi (pa mí láṣẹ láti lọ). Ó sì máa tọ́ mi sọ́nà (láti dé ibẹ̀).

﴿رَبِّ هَبْ لِي مِنَ الصَّالِحِينَ﴾

Olúwa mi, ta mí lọ́rẹ ọmọ nínú àwọn ẹni rere."

﴿فَبَشَّرْنَاهُ بِغُلَامٍ حَلِيمٍ﴾

A sì fún un ní ìró ìdùnnú (nípa bíbí) ọmọkùnrin aláfaradà.

﴿فَلَمَّا بَلَغَ مَعَهُ السَّعْيَ قَالَ يَا بُنَيَّ إِنِّي أَرَىٰ فِي الْمَنَامِ أَنِّي أَذْبَحُكَ فَانْظُرْ مَاذَا تَرَىٰ ۚ قَالَ يَا أَبَتِ افْعَلْ مَا تُؤْمَرُ ۖ سَتَجِدُنِي إِنْ شَاءَ اللَّهُ مِنَ الصَّابِرِينَ﴾

Nígbà tí (ọmọ náà) dàgbà, tí ó tó bá (bàbá rẹ̀) ṣe iṣẹ́, (bàbá rẹ̀) sọ pé: "Ọmọ mi, dájúdájú èmi lá àlá pé dájúdájú mò ń dúńbú rẹ. Nítorí náà, wòye sí i, kí ni o rí sí i." Ó sọ pé: "Bàbá mi, ṣe ohun tí Wọ́n pa láṣẹ fún ọ. O máa bá mi nínú àwọn onísùúrù, tí Allāhu bá fẹ́."

﴿فَلَمَّا أَسْلَمَا وَتَلَّهُ لِلْجَبِينِ﴾

Nígbà tí àwọn méjèèjì juwọ́ jusẹ̀ sílẹ̀, tí (Ànábì ’Ibrọ̄hīm) sì dojú (ọmọ) rẹ̀ bolẹ̀,

﴿وَنَادَيْنَاهُ أَنْ يَا إِبْرَاهِيمُ﴾

A pè é (báyìí) pé, ’Ibrọ̄hīm,

﴿قَدْ صَدَّقْتَ الرُّؤْيَا ۚ إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

o kúkú ti mú àlá náà ṣẹ. Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿إِنَّ هَٰذَا لَهُوَ الْبَلَاءُ الْمُبِينُ﴾

Dájúdájú èyí, òhun ni àdánwò pọ́nńbélé.

﴿وَفَدَيْنَاهُ بِذِبْحٍ عَظِيمٍ﴾

A sì fi àgbò ńlá ṣèràpadà rẹ̀.

﴿وَتَرَكْنَا عَلَيْهِ فِي الْآخِرِينَ﴾

A tún fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.

﴿سَلَامٌ عَلَىٰ إِبْرَاهِيمَ﴾

Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm.

﴿كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

Báyẹn ni A ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿إِنَّهُ مِنْ عِبَادِنَا الْمُؤْمِنِينَ﴾

Dájúdájú ó wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَبَشَّرْنَاهُ بِإِسْحَاقَ نَبِيًّا مِنَ الصَّالِحِينَ﴾

A tún fún un ní ìró ìdùnnú (nípa bíbí) ’Ishāƙ, (ó máa jẹ́) Ànábì. (Ó sì máa wà) nínú àwọn ẹni rere.

﴿وَبَارَكْنَا عَلَيْهِ وَعَلَىٰ إِسْحَاقَ ۚ وَمِنْ ذُرِّيَّتِهِمَا مُحْسِنٌ وَظَالِمٌ لِنَفْسِهِ مُبِينٌ﴾

Àti pé A fún òun àti ’Ishāƙ ní ìbùkún. Ẹni rere àti alábòsí pọ́nńbélé (t’ó ń ṣàbòsí sí) ẹ̀mí ara rẹ̀ wà nínú àrọ́mọdọ́mọ àwọn méjèèjì.

﴿وَلَقَدْ مَنَنَّا عَلَىٰ مُوسَىٰ وَهَارُونَ﴾

Dájúdájú A ṣoore fún (Ànábì) Mūsā àti Hārūn.

﴿وَنَجَّيْنَاهُمَا وَقَوْمَهُمَا مِنَ الْكَرْبِ الْعَظِيمِ﴾

A gba àwọn méjèèjì àti ìjọ àwọn méjèèjì là kúrò nínú ìbànújẹ́ ńlá.

﴿وَنَصَرْنَاهُمْ فَكَانُوا هُمُ الْغَالِبِينَ﴾

A tún ṣàrànṣe fún wọn. Àwọn ni wọ́n jẹ́ olùborí (ọ̀tá wọn).

﴿وَآتَيْنَاهُمَا الْكِتَابَ الْمُسْتَبِينَ﴾

A sì fún àwọn méjèèjì ní Tírà t’ó yanjú.

﴿وَهَدَيْنَاهُمَا الصِّرَاطَ الْمُسْتَقِيمَ﴾

A tún fi àwọn méjèèjì mọ̀nà tààrà.

﴿وَتَرَكْنَا عَلَيْهِمَا فِي الْآخِرِينَ﴾

A fún àwọn méjèèjì ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.

﴿سَلَامٌ عَلَىٰ مُوسَىٰ وَهَارُونَ﴾

Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) Mūsā àti Hārūn.

﴿إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿إِنَّهُمَا مِنْ عِبَادِنَا الْمُؤْمِنِينَ﴾

Dájúdájú àwọn méjèèjì wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَإِنَّ إِلْيَاسَ لَمِنَ الْمُرْسَلِينَ﴾

Dájúdájú (Ànábì) ’Ilyās wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.

﴿إِذْ قَالَ لِقَوْمِهِ أَلَا تَتَّقُونَ﴾

(Ẹ rántí) nígbà tí ó sọ fún ìjọ rẹ̀ pé: "Ṣé ẹ ò níí bẹ̀rù Allāhu ni?

﴿أَتَدْعُونَ بَعْلًا وَتَذَرُونَ أَحْسَنَ الْخَالِقِينَ﴾

Ṣé ẹ óò máa pe òrìṣà kan, ẹ sì máa fi Ẹni t’Ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá sílẹ̀,

﴿اللَّهَ رَبَّكُمْ وَرَبَّ آبَائِكُمُ الْأَوَّلِينَ﴾

(ẹ̀ ń fi) Allāhu (sílẹ̀), Olúwa yín àti Olúwa àwọn bàbá yín, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"

﴿فَكَذَّبُوهُ فَإِنَّهُمْ لَمُحْضَرُونَ﴾

Wọ́n sì pè é ní òpùrọ́. Nítorí náà, wọ́n máa mú wọn wá sínú Iná.

﴿إِلَّا عِبَادَ اللَّهِ الْمُخْلَصِينَ﴾

Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.

﴿وَتَرَكْنَا عَلَيْهِ فِي الْآخِرِينَ﴾

A fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.

﴿سَلَامٌ عَلَىٰ إِلْ يَاسِينَ﴾

Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) ’Ilyās.

﴿إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿إِنَّهُ مِنْ عِبَادِنَا الْمُؤْمِنِينَ﴾

Dájúdájú ó wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَإِنَّ لُوطًا لَمِنَ الْمُرْسَلِينَ﴾

Dájúdájú (Ànábì) Lūt wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.

﴿إِذْ نَجَّيْنَاهُ وَأَهْلَهُ أَجْمَعِينَ﴾

(Ẹ rántí) nígbà tí A gba òun àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀ là.

﴿إِلَّا عَجُوزًا فِي الْغَابِرِينَ﴾

Àyàfi arúgbóbìnrin kan tí ó wà nínú àwọn t’ó ṣẹ́ kù lẹ́yìn (láààrin àwọn tí A parẹ́).

﴿ثُمَّ دَمَّرْنَا الْآخَرِينَ﴾

Lẹ́yìn náà, A pa àwọn yòókù run.

﴿وَإِنَّكُمْ لَتَمُرُّونَ عَلَيْهِمْ مُصْبِحِينَ﴾

Dájúdájú ẹ̀yin náà kúkú ń gba ọ̀dọ̀ wọn kọjá láàárọ̀-láàárọ̀

﴿وَبِاللَّيْلِ ۗ أَفَلَا تَعْقِلُونَ﴾

àti ní alaalẹ́. Ṣé ẹ ò níí ṣe làákàyè ni?

﴿وَإِنَّ يُونُسَ لَمِنَ الْمُرْسَلِينَ﴾

Dájúdájú (Ànábì) Yūnus kúkú wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.

﴿إِذْ أَبَقَ إِلَى الْفُلْكِ الْمَشْحُونِ﴾

(Ẹ rántí) nígbà tí ó sá lọ sínú ọkọ̀ ojú-omi t’ó kún kẹ́kẹ́.

﴿فَسَاهَمَ فَكَانَ مِنَ الْمُدْحَضِينَ﴾

Ó sì bá wọn muje pọ̀. Ó sì wà nínú àwọn tí aje ṣí mọ́ lórí.

﴿فَالْتَقَمَهُ الْحُوتُ وَهُوَ مُلِيمٌ﴾

Nítorí náà, ẹja gbé e mì; ó sì ń dá ara rẹ̀ lẹ́bi.

﴿فَلَوْلَا أَنَّهُ كَانَ مِنَ الْمُسَبِّحِينَ﴾

Nítorí náà, tí kò bá jẹ́ pé ó wà nínú àwọn olùṣàfọ̀mọ́ fún Allāhu,

﴿لَلَبِثَ فِي بَطْنِهِ إِلَىٰ يَوْمِ يُبْعَثُونَ﴾

dájúdájú ìbá wà nínú ẹja títí di ọjọ́ tí wọn yóò gbé ẹ̀dá dìde.

﴿۞ فَنَبَذْنَاهُ بِالْعَرَاءِ وَهُوَ سَقِيمٌ﴾

Nítorí náà, A jù ú sí orí ilẹ́ gban̄sasa létí omi. Ó sì jẹ́ aláìlera.

﴿وَأَنْبَتْنَا عَلَيْهِ شَجَرَةً مِنْ يَقْطِينٍ﴾

A sì mú igi Yẹƙtīn hù jáde láti ṣíji bò ó.

﴿وَأَرْسَلْنَاهُ إِلَىٰ مِائَةِ أَلْفٍ أَوْ يَزِيدُونَ﴾

A tún rán an níṣẹ́ sí ọ̀kẹ́ márùn-ún (ènìyàn) tàbí kí wọ́n lékún sí i.

﴿فَآمَنُوا فَمَتَّعْنَاهُمْ إِلَىٰ حِينٍ﴾

Wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo. A sì fún wọn ní ìgbádùn títí di ìgbà díẹ̀.

﴿فَاسْتَفْتِهِمْ أَلِرَبِّكَ الْبَنَاتُ وَلَهُمُ الْبَنُونَ﴾

Bi wọ́n léèrè wò pé: "Ṣé Olúwa rẹ l’ó ni àwọn ọmọbìnrin, tiwọn sì ni ọmọkùnrin?

﴿أَمْ خَلَقْنَا الْمَلَائِكَةَ إِنَاثًا وَهُمْ شَاهِدُونَ﴾

Tàbí A dá àwọn mọlāika ní obìnrin, tí àwọn sì jẹ́ ẹlẹ́rìí?"

﴿أَلَا إِنَّهُمْ مِنْ إِفْكِهِمْ لَيَقُولُونَ﴾

Gbọ́, nínú irọ́ wọn ni pé dájúdájú wọ́n ń wí pé:

﴿وَلَدَ اللَّهُ وَإِنَّهُمْ لَكَاذِبُونَ﴾

(Allāhu búra pẹ̀lú) àwọn mọlāika olùtò-lọ́wọ̀ọ̀wọ́ tààrà;

﴿أَصْطَفَى الْبَنَاتِ عَلَى الْبَنِينَ﴾

Ṣé (Allāhu) ṣẹ̀ṣà àwọn ọmọbìnrin lórí àwọn ọmọkùnrin ni?

﴿مَا لَكُمْ كَيْفَ تَحْكُمُونَ﴾

Kí l’ó ń ṣe yín tí ẹ fi ń dájọ́ báyìí?

﴿أَفَلَا تَذَكَّرُونَ﴾

Ṣé ẹ ò níí lo ìrántí ni?

﴿أَمْ لَكُمْ سُلْطَانٌ مُبِينٌ﴾

Tàbí ẹ ní ẹ̀rí t’ó yanjú lọ́wọ́ ni?

﴿فَأْتُوا بِكِتَابِكُمْ إِنْ كُنْتُمْ صَادِقِينَ﴾

Ẹ mú tírà yín wà nígbà náà tí ẹ bá jẹ́ olódodo.

﴿وَجَعَلُوا بَيْنَهُ وَبَيْنَ الْجِنَّةِ نَسَبًا ۚ وَلَقَدْ عَلِمَتِ الْجِنَّةُ إِنَّهُمْ لَمُحْضَرُونَ﴾

Wọ́n tún fi ìbátan sáààrin (Allāhu) àti àlùjànnú! Àwọn àlùjànnú sì ti mọ̀ pé dájúdájú wọ́n kúkú máa mú àwọn wá sínú Iná ni.

﴿سُبْحَانَ اللَّهِ عَمَّا يَصِفُونَ﴾

Mímọ́ ni fún Allāhu tayọ ohun tí wọ́n ń fi ròyìn (Rẹ̀).

﴿إِلَّا عِبَادَ اللَّهِ الْمُخْلَصِينَ﴾

Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.

﴿فَإِنَّكُمْ وَمَا تَعْبُدُونَ﴾

Dájúdájú ẹ̀yin àti n̄ǹkan tí ẹ̀ ń jọ́sìn fún (lẹ́yìn Allāhu),

﴿مَا أَنْتُمْ عَلَيْهِ بِفَاتِنِينَ﴾

ẹ ò lè fi ṣi ẹnì kan kan lọ́nà

﴿إِلَّا مَنْ هُوَ صَالِ الْجَحِيمِ﴾

àfi ẹni tí ó bá fẹ́ wọ inú iná Jẹhīm.

﴿وَمَا مِنَّا إِلَّا لَهُ مَقَامٌ مَعْلُومٌ﴾

Kò sí ẹnì kan nínú àwa (mọlāika) àfi kí ó ní ibùdúró tí wọ́n ti mọ̀.

﴿وَإِنَّا لَنَحْنُ الصَّافُّونَ﴾

Dájúdájú àwa, a kúkú wà ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.

﴿وَإِنَّا لَنَحْنُ الْمُسَبِّحُونَ﴾

Àti pé dájúdájú àwa, àwa kúkú ni olùṣàfọ̀mọ́ (fún Allāhu).

﴿وَإِنْ كَانُوا لَيَقُولُونَ﴾

Wọ́n kúkú ń wí pé:

﴿لَوْ أَنَّ عِنْدَنَا ذِكْرًا مِنَ الْأَوَّلِينَ﴾

"Tí ó bá jẹ́ pé dájúdájú a bá ní (tírà) ìrántí kan nínú (àwọn tírà) àwọn ẹni àkọ́kọ́,

﴿لَكُنَّا عِبَادَ اللَّهِ الْمُخْلَصِينَ﴾

dájúdájú àwa ìbá jẹ́ ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà."

﴿فَكَفَرُوا بِهِ ۖ فَسَوْفَ يَعْلَمُونَ﴾

Ṣùgbọ́n wọ́n ṣàì gbàgbọ́ nínú (Allāhu). Láìpẹ́ wọ́n máa mọ̀.

﴿وَلَقَدْ سَبَقَتْ كَلِمَتُنَا لِعِبَادِنَا الْمُرْسَلِينَ﴾

Dájúdájú ọ̀rọ̀ Wa ti ṣíwájú fún àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn Òjíṣẹ́.

﴿إِنَّهُمْ لَهُمُ الْمَنْصُورُونَ﴾

Dájúdájú àwọn, àwọn l’a kúkú máa ṣàrànṣe fún.

﴿وَإِنَّ جُنْدَنَا لَهُمُ الْغَالِبُونَ﴾

Àti pé dájúdájú àwọn ọmọ ogun Wa, àwọn kúkú ni olùborí.

﴿فَتَوَلَّ عَنْهُمْ حَتَّىٰ حِينٍ﴾

Nítorí náà, ṣẹ́rí kúrò lọ́dọ̀ wọn fún ìgbà díẹ̀.

﴿وَأَبْصِرْهُمْ فَسَوْفَ يُبْصِرُونَ﴾

Àti pé máa wò wọ́n níran ná, àwọn náà ń bọ̀ wá ríran wò.

﴿أَفَبِعَذَابِنَا يَسْتَعْجِلُونَ﴾

Ṣé ìyà Wa ni wọ́n ń wá pẹ̀lú ìkánjú?

﴿فَإِذَا نَزَلَ بِسَاحَتِهِمْ فَسَاءَ صَبَاحُ الْمُنْذَرِينَ﴾

Nígbà tí ó bá sọ̀kalẹ̀ sí agboolé wọn, òwúrọ̀ ọjọ́ náà yó sì burú fún àwọn ẹni-akìlọ̀-fún.

﴿وَتَوَلَّ عَنْهُمْ حَتَّىٰ حِينٍ﴾

Kúrò lọ́dọ̀ wọn títí di ìgbà kan ná.

﴿وَأَبْصِرْ فَسَوْفَ يُبْصِرُونَ﴾

Àti pé máa wò wọ́n níran ná, àwọn náà ń bọ̀ wá ríran wò.

﴿سُبْحَانَ رَبِّكَ رَبِّ الْعِزَّةِ عَمَّا يَصِفُونَ﴾

Mímọ́ ni fún Olúwa rẹ, Olúwa agbára, tayọ ohun tí wọ́n ń fi ròyìn (Rẹ̀).

﴿وَسَلَامٌ عَلَى الْمُرْسَلِينَ﴾

Kí àlàáfíà máa bá àwọn Òjíṣẹ́

﴿وَالْحَمْدُ لِلَّهِ رَبِّ الْعَالَمِينَ﴾

Gbogbo ọpẹ́ ń jẹ́ ti Allāhu, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: