النجم

تفسير سورة النجم

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالنَّجْمِ إِذَا هَوَىٰ﴾

(Allāhu búra pẹ̀lú) ìràwọ̀ nígbà tí ó bá jábọ́.

﴿مَا ضَلَّ صَاحِبُكُمْ وَمَا غَوَىٰ﴾

Ẹni yín kò ṣìnà, kò sì sọnù.

﴿وَمَا يَنْطِقُ عَنِ الْهَوَىٰ﴾

Àti pé kò níí sọ̀rọ̀ ìfẹ́-inú.

﴿إِنْ هُوَ إِلَّا وَحْيٌ يُوحَىٰ﴾

Kò níí sọ ohun kan tayọ ìmísí tí A fi ránṣẹ́ sí i.

﴿عَلَّمَهُ شَدِيدُ الْقُوَىٰ﴾

Alágbára (ìyẹn, mọlāika Jibrīl) l’ó kọ́ ọ ní ìmọ̀ (al-Ƙur’ān).

﴿ذُو مِرَّةٍ فَاسْتَوَىٰ﴾

Ó ní àlàáfíà t’ó péye. Nítorí náà, ó dúró wámúwámú,

﴿وَهُوَ بِالْأُفُقِ الْأَعْلَىٰ﴾

nígbà tí ó wà nínú òfurufú lókè pátápátá.

﴿ثُمَّ دَنَا فَتَدَلَّىٰ﴾

Lẹ́yìn náà, ó sún mọ́ (Ànábì). Ó sì sọ̀kalẹ̀ (tọ̀ ọ́ wá).

﴿فَكَانَ قَابَ قَوْسَيْنِ أَوْ أَدْنَىٰ﴾

(Àlàfo ààrin àwọn méjèèjì) sì tó ìwọ̀n ọrún ọfà méjì, tàbí kí ó kéré (sí ìyẹn).

﴿فَأَوْحَىٰ إِلَىٰ عَبْدِهِ مَا أَوْحَىٰ﴾

Allāhu sì fún ẹrúsìn Rẹ̀ ní ìmísí t’Ó fún un.

﴿مَا كَذَبَ الْفُؤَادُ مَا رَأَىٰ﴾

Ọkàn (Ànábì) kò parọ́ ohun t’ó rí.

﴿أَفَتُمَارُونَهُ عَلَىٰ مَا يَرَىٰ﴾

Ṣé ẹ óò jà á níyàn nípa ohun t’ó rí ni?

﴿وَلَقَدْ رَآهُ نَزْلَةً أُخْرَىٰ﴾

Àti pé dájúdájú ó rí i nígbà kejì

﴿عِنْدَ سِدْرَةِ الْمُنْتَهَىٰ﴾

níbi igi sidirah al-Muntahā,

﴿عِنْدَهَا جَنَّةُ الْمَأْوَىٰ﴾

nítòsí rẹ̀ ni Ọgbà Ibùgbé (gbére) wà.

﴿إِذْ يَغْشَى السِّدْرَةَ مَا يَغْشَىٰ﴾

(Rántí) nígbà tí ohun t’ó bo igi Sidirah bò ó mọ́lẹ̀.

﴿مَا زَاغَ الْبَصَرُ وَمَا طَغَىٰ﴾

Ojú (Ànábì) kò yẹ̀, kò sì tayọ ẹnu-àlà.

﴿لَقَدْ رَأَىٰ مِنْ آيَاتِ رَبِّهِ الْكُبْرَىٰ﴾

Dájúdájú ó rí nínú àwọn àmì Olúwa rẹ̀, t’ó tóbi jùlọ.

﴿أَفَرَأَيْتُمُ اللَّاتَ وَالْعُزَّىٰ﴾

Ẹ sọ fún mi nípa òrìṣà Lāt àti òrìṣà ‘Uzzā,

﴿وَمَنَاةَ الثَّالِثَةَ الْأُخْرَىٰ﴾

àti Mọnāh, òrìṣà kẹta mìíràn.

﴿أَلَكُمُ الذَّكَرُ وَلَهُ الْأُنْثَىٰ﴾

Ṣé ọmọkùnrin ni tiyín, ọmọbìnrin sì ni tiRẹ̀?

﴿تِلْكَ إِذًا قِسْمَةٌ ضِيزَىٰ﴾

Ìpín àbòsí nìyẹn nígbà náà.

﴿إِنْ هِيَ إِلَّا أَسْمَاءٌ سَمَّيْتُمُوهَا أَنْتُمْ وَآبَاؤُكُمْ مَا أَنْزَلَ اللَّهُ بِهَا مِنْ سُلْطَانٍ ۚ إِنْ يَتَّبِعُونَ إِلَّا الظَّنَّ وَمَا تَهْوَى الْأَنْفُسُ ۖ وَلَقَدْ جَاءَهُمْ مِنْ رَبِّهِمُ الْهُدَىٰ﴾

(Àwọn orúkọ òrìṣà wọ̀nyẹn) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe àwọn orúkọ kan tí ẹ̀yin àti àwọn bàbá yín fi sọ (àwọn òrìṣà yín fúnra yín). Allāhu kò sì sọ ẹ̀rí ọ̀rọ̀ kan kalẹ̀ nípa rẹ̀. Wọn kò sì tẹ̀lé kiní kan bí kò ṣe àròsọ àti ohun tí ẹ̀mí (wọn) ń fẹ́. Ìmọ̀nà kúkú ti dé bá wọn láti ọ̀dọ̀ Olúwa wọn.

﴿أَمْ لِلْإِنْسَانِ مَا تَمَنَّىٰ﴾

Tàbí ti ènìyàn ni n̄ǹkan t’ó bá ń fẹ́!

﴿فَلِلَّهِ الْآخِرَةُ وَالْأُولَىٰ﴾

Ti Allāhu sì ni ọ̀run àti ayé.

﴿۞ وَكَمْ مِنْ مَلَكٍ فِي السَّمَاوَاتِ لَا تُغْنِي شَفَاعَتُهُمْ شَيْئًا إِلَّا مِنْ بَعْدِ أَنْ يَأْذَنَ اللَّهُ لِمَنْ يَشَاءُ وَيَرْضَىٰ﴾

Àti pé mélòó mélòó nínú àwọn mọlāika t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀, tí ìṣìpẹ̀ wọn kò níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ kiní kan àyàfi lẹ́yìn ìgbà tí Allāhu bá yọ̀ǹda fún ẹni tí Ó bá fẹ́, tí Ó sì yọ́nú sí.

﴿إِنَّ الَّذِينَ لَا يُؤْمِنُونَ بِالْآخِرَةِ لَيُسَمُّونَ الْمَلَائِكَةَ تَسْمِيَةَ الْأُنْثَىٰ﴾

Dájúdájú àwọn tí kò ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, àwọn ni wọ́n ń fún àwọn mọlāika ní orúkọ obìnrin.

﴿وَمَا لَهُمْ بِهِ مِنْ عِلْمٍ ۖ إِنْ يَتَّبِعُونَ إِلَّا الظَّنَّ ۖ وَإِنَّ الظَّنَّ لَا يُغْنِي مِنَ الْحَقِّ شَيْئًا﴾

Kò sí ìmọ̀ kan fún wọn nípa rẹ̀. Wọn kò sì tẹ̀lé kiní kan bí kò ṣe àròsọ. Dájúdájú àròsọ kò sì níí rọrọ̀ kiní kan lára òdodo.

﴿فَأَعْرِضْ عَنْ مَنْ تَوَلَّىٰ عَنْ ذِكْرِنَا وَلَمْ يُرِدْ إِلَّا الْحَيَاةَ الدُّنْيَا﴾

Nítorí náà, ṣẹ́rí kúrò ní ọ̀dọ̀ ẹni t’ó kẹ̀yìn sí ìrántí Wa, tí kò sì gbèrò kiní kan àfi ìṣẹ̀mí ayé.

﴿ذَٰلِكَ مَبْلَغُهُمْ مِنَ الْعِلْمِ ۚ إِنَّ رَبَّكَ هُوَ أَعْلَمُ بِمَنْ ضَلَّ عَنْ سَبِيلِهِ وَهُوَ أَعْلَمُ بِمَنِ اهْتَدَىٰ﴾

Ìyẹn ni òdíwọ̀n (àti òpin) ìmọ̀ wọn. Dájúdájú Olúwa rẹ, Ó nímọ̀ jùlọ nípa ẹni t’ó ṣìnà kúrò lójú ọ̀nà Rẹ̀. Ó sì nímọ̀ jùlọ nípa ẹni t’ó mọ̀nà.

﴿وَلِلَّهِ مَا فِي السَّمَاوَاتِ وَمَا فِي الْأَرْضِ لِيَجْزِيَ الَّذِينَ أَسَاءُوا بِمَا عَمِلُوا وَيَجْزِيَ الَّذِينَ أَحْسَنُوا بِالْحُسْنَى﴾

Ti Allāhu ni ohunkóhun t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀ nítorí kí Ó lè san àwọn t’ó ṣe iṣẹ́ aburú ní ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe níṣẹ́ àti nítorí kí Ó lè san àwọn t’ó ṣe iṣẹ́ rere ni ẹ̀san rere.

﴿الَّذِينَ يَجْتَنِبُونَ كَبَائِرَ الْإِثْمِ وَالْفَوَاحِشَ إِلَّا اللَّمَمَ ۚ إِنَّ رَبَّكَ وَاسِعُ الْمَغْفِرَةِ ۚ هُوَ أَعْلَمُ بِكُمْ إِذْ أَنْشَأَكُمْ مِنَ الْأَرْضِ وَإِذْ أَنْتُمْ أَجِنَّةٌ فِي بُطُونِ أُمَّهَاتِكُمْ ۖ فَلَا تُزَكُّوا أَنْفُسَكُمْ ۖ هُوَ أَعْلَمُ بِمَنِ اتَّقَىٰ﴾

Àwọn t’ó ń jìnnà sí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá ńlá àti ìwà ìbàjẹ́ àyàfi àwọn ẹ̀ṣẹ̀ pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́, dájúdájú Olúwa rẹ gbòòrò ní àforíjìn. Ó nímọ̀ jùlọ nípa yín nígbà tí Ó ṣẹ̀dá yín láti inú ilẹ̀ àti nígbà tí ẹ wà ní ọlẹ̀ nínú àwọn ikùn ìyá yín. Nítorí náà, ẹ má ṣe fọra yín mọ́. Ó nímọ̀ jùlọ nípa ẹni t’ó bẹ̀rù (Rẹ̀).

﴿أَفَرَأَيْتَ الَّذِي تَوَلَّىٰ﴾

Sọ fún mi nípa ẹni t’ó gbúnrí (kúrò níbi òdodo),

﴿وَأَعْطَىٰ قَلِيلًا وَأَكْدَىٰ﴾

tí ó fi díẹ̀ tọrẹ, tí ó sì di ìyókù mọ́wọ́!

﴿أَعِنْدَهُ عِلْمُ الْغَيْبِ فَهُوَ يَرَىٰ﴾

Ṣé ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ wà ní ọ̀dọ̀ rẹ, tí ó sì ń rí i (pé ẹlòmíìràn l’ó ma bá òun jìyà lọ́run)?

﴿أَمْ لَمْ يُنَبَّأْ بِمَا فِي صُحُفِ مُوسَىٰ﴾

Tàbí wọn kò fún un ní ìró ohun t’ó wà nínú tírà (Ànábì) Mūsā ni,

﴿وَإِبْرَاهِيمَ الَّذِي وَفَّىٰ﴾

àti (tírà Ànábì) ’Ibrọ̄hīm, ẹni t’ó mú (òfin Allāhu) ṣẹ,

﴿أَلَّا تَزِرُ وَازِرَةٌ وِزْرَ أُخْرَىٰ﴾

pé dájúdájú ẹlẹ́rù-ẹ̀ṣẹ̀ kan kò níí ru ẹrù-ẹ̀ṣẹ̀ ẹlòmíìràn.

﴿وَأَنْ لَيْسَ لِلْإِنْسَانِ إِلَّا مَا سَعَىٰ﴾

Àti pé kò sí kiní kan fún ènìyàn àfi ohun t’ó ṣe níṣẹ́.

﴿وَأَنَّ سَعْيَهُ سَوْفَ يُرَىٰ﴾

Àti pé dájúdájú iṣẹ́ rẹ̀, láìpẹ́ wọ́n máa fi hàn án.

﴿ثُمَّ يُجْزَاهُ الْجَزَاءَ الْأَوْفَىٰ﴾

Lẹ́yìn náà, wọ́n máa san án ní ẹ̀san rẹ̀, ní ẹ̀san t’ó kún jùlọ.

﴿وَأَنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ الْمُنْتَهَىٰ﴾

Àti pé dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin (ìrìn-àjò ẹ̀dá).

﴿وَأَنَّهُ هُوَ أَضْحَكَ وَأَبْكَىٰ﴾

Dájúdájú Òun l’Ó ń pa (ẹ̀dá) ní ẹ̀rín. Ó sì ń pa (ẹ̀dá) ní ẹkún.

﴿وَأَنَّهُ هُوَ أَمَاتَ وَأَحْيَا﴾

Dájúdájú Òun l’Ó ń sọ (ẹ̀dá) di òkú. Ó sì ń sọ (ẹ̀dá) di alààyè.

﴿وَأَنَّهُ خَلَقَ الزَّوْجَيْنِ الذَّكَرَ وَالْأُنْثَىٰ﴾

Dájúdájú Òun l’Ó dá ẹ̀dá ní oríṣi méjì, ọkùnrin àti obìnrin,

﴿مِنْ نُطْفَةٍ إِذَا تُمْنَىٰ﴾

láti ara àtọ̀ nígbà tí wọ́n bá dà á sínú àpòlùkẹ́.

﴿وَأَنَّ عَلَيْهِ النَّشْأَةَ الْأُخْرَىٰ﴾

Dájúdájú Òun l’Ó máa ṣe ìṣẹ̀dá ìkẹ́yìn fún àjíǹde,

﴿وَأَنَّهُ هُوَ أَغْنَىٰ وَأَقْنَىٰ﴾

Dájúdájú Òun l’Ó ń ṣe púpọ̀, Ó sì ń ṣe kékeré (oore fún ẹ̀dá).

﴿وَأَنَّهُ هُوَ رَبُّ الشِّعْرَىٰ﴾

Dájúdájú Òun sì ni Olúwa ìràwọ̀ Ṣi‘rọ̄ (tí wọ́n sọ di òrìṣà).

﴿وَأَنَّهُ أَهْلَكَ عَادًا الْأُولَىٰ﴾

Dájúdájú Òun l’Ó pa ìran ‘Ād rẹ́, àwọn ẹni àkọ́kọ́;

﴿وَثَمُودَ فَمَا أَبْقَىٰ﴾

àti ìran Thamūd, kò sì ṣẹ́ wọn kù;

﴿وَقَوْمَ نُوحٍ مِنْ قَبْلُ ۖ إِنَّهُمْ كَانُوا هُمْ أَظْلَمَ وَأَطْغَىٰ﴾

àti ìjọ Nūh t’ó ṣíwájú (wọn), dájúdájú wọ́n jẹ́ alábòsí jùlọ, wọ́n sì tayọ ẹnu-àlà jùlọ;

﴿وَالْمُؤْتَفِكَةَ أَهْوَىٰ﴾

àti ìlú tí wọ́n dàwó (ìlú Ànábì Lūt) t’Ó yẹ̀ lulẹ̀ (láti òkè).

﴿فَغَشَّاهَا مَا غَشَّىٰ﴾

Ohun t’ó bò wọ́n mọ́lẹ̀ bò wọ́n mọ́lẹ̀.

﴿فَبِأَيِّ آلَاءِ رَبِّكَ تَتَمَارَىٰ﴾

Nítorí náà, èwo nínú ìdẹ̀ra Olúwa rẹ ni ìwọ (ènìyàn) ń jà níyàn?

﴿هَٰذَا نَذِيرٌ مِنَ النُّذُرِ الْأُولَىٰ﴾

Èyí ni ìkìlọ̀ kan nínú àwọn ìkìlọ̀ àkọ́kọ́.

﴿أَزِفَتِ الْآزِفَةُ﴾

Ohun t’ó súnmọ́ súnmọ́.

﴿لَيْسَ لَهَا مِنْ دُونِ اللَّهِ كَاشِفَةٌ﴾

Lẹ́yìn Allāhu, kò sí ẹni t’ó lè ṣàfi hàn (Àkókò náà).

﴿أَفَمِنْ هَٰذَا الْحَدِيثِ تَعْجَبُونَ﴾

Ṣé ọ̀rọ̀ yìí l’ó ń ṣe yín ní kàyéfì?

﴿وَتَضْحَكُونَ وَلَا تَبْكُونَ﴾

Ẹ̀ ń rẹ́rìn-ín, ẹ ò sì sunkún!

﴿وَأَنْتُمْ سَامِدُونَ﴾

Afọ́nú-fọ́ra ni yín.

﴿فَاسْجُدُوا لِلَّهِ وَاعْبُدُوا ۩﴾

Nítorí náà, ẹ forí kanlẹ̀ fún Allāhu, kí ẹ jọ́sìn (fún Un).

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: