الإنشقاق

تفسير سورة الإنشقاق

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ إِذَا السَّمَاءُ انْشَقَّتْ﴾

Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ

﴿وَأَذِنَتْ لِرَبِّهَا وَحُقَّتْ﴾

- ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ –

﴿وَإِذَا الْأَرْضُ مُدَّتْ﴾

àti nígbà tí A bá fẹ ilẹ̀ lójú,

﴿وَأَلْقَتْ مَا فِيهَا وَتَخَلَّتْ﴾

ó máa ju ohun tí ó wà nínú rẹ̀ síta, ó sì máa pa sófo

﴿وَأَذِنَتْ لِرَبِّهَا وَحُقَّتْ﴾

– ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ – (ní ọjọ́ yẹn ni ẹ̀dá máa rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀)

﴿يَا أَيُّهَا الْإِنْسَانُ إِنَّكَ كَادِحٌ إِلَىٰ رَبِّكَ كَدْحًا فَمُلَاقِيهِ﴾

Ìwọ ènìyàn dájúdájú ìwọ ń ṣe iṣẹ́ kárakára ní iṣẹ́ àṣepàdé Olúwa rẹ. O sì máa mú un pàdé Rẹ̀.

﴿فَأَمَّا مَنْ أُوتِيَ كِتَابَهُ بِيَمِينِهِ﴾

Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀,

﴿فَسَوْفَ يُحَاسَبُ حِسَابًا يَسِيرًا﴾

láìpẹ́ A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ (rẹ̀) ní ìṣírò ìrọ̀rùn.

﴿وَيَنْقَلِبُ إِلَىٰ أَهْلِهِ مَسْرُورًا﴾

Ó sì máa padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra) lẹ́ni ìdùnnú.

﴿وَأَمَّا مَنْ أُوتِيَ كِتَابَهُ وَرَاءَ ظَهْرِهِ﴾

Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ láti ẹ̀yìn rẹ̀,

﴿فَسَوْفَ يَدْعُو ثُبُورًا﴾

láìpẹ́ ó máa kígbe ìparun.

﴿وَيَصْلَىٰ سَعِيرًا﴾

Ó sì máa wọ inú Iná t’ó ń jò fòfò.

﴿إِنَّهُ كَانَ فِي أَهْلِهِ مَسْرُورًا﴾

Dájúdájú ó ti wà láààrin àwọn ènìyàn rẹ̀ lẹ́ni ìdùnnú (sí àìgbàgbọ́ nílé ayé).

﴿إِنَّهُ ظَنَّ أَنْ لَنْ يَحُورَ﴾

Dájúdájú ó lérò pé òun kò níí padà (sí ọ̀dọ̀ Allāhu ni).

﴿بَلَىٰ إِنَّ رَبَّهُ كَانَ بِهِ بَصِيرًا﴾

Rárá (ó máa padà). Dájúdájú Olúwa rẹ̀ jẹ́ Olùríran nípa rẹ̀.

﴿فَلَا أُقْسِمُ بِالشَّفَقِ﴾

Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwòǹpapa.

﴿وَاللَّيْلِ وَمَا وَسَقَ﴾

Mo tún búra pẹ̀lú òru àti ohun tí ó kó jọ sínú rẹ̀.

﴿وَالْقَمَرِ إِذَا اتَّسَقَ﴾

Mo tún búra pẹ̀lú òṣùpá nígbà tí ó bá dégbá (pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀).

﴿لَتَرْكَبُنَّ طَبَقًا عَنْ طَبَقٍ﴾

Dájúdájú ẹ̀yin yóò máa bọ́ sínú wàhálà kan láti inú wàhálà kan.

﴿فَمَا لَهُمْ لَا يُؤْمِنُونَ﴾

Kí l’ó ṣe wọ́n ná tí wọn kò fi gbàgbọ́ ní òdodo?

﴿وَإِذَا قُرِئَ عَلَيْهِمُ الْقُرْآنُ لَا يَسْجُدُونَ ۩﴾

Nígbà tí wọ́n bá sì ké al-Ƙur’ān fún wọn, wọn kò níí forí kanlẹ̀.

﴿بَلِ الَّذِينَ كَفَرُوا يُكَذِّبُونَ﴾

Rárá, ńṣe ni àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ ń pè é nírọ́.

﴿وَاللَّهُ أَعْلَمُ بِمَا يُوعُونَ﴾

Allāhu sì nímọ̀ jùlọ nípa ohun tí wọ́n ń fi pamọ́ (sínú ọkàn wọn).

﴿فَبَشِّرْهُمْ بِعَذَابٍ أَلِيمٍ﴾

Nítorí náà, fún wọn ní ìró ìyà ẹlẹ́ta-eléro.

﴿إِلَّا الَّذِينَ آمَنُوا وَعَمِلُوا الصَّالِحَاتِ لَهُمْ أَجْرٌ غَيْرُ مَمْنُونٍ﴾

Àyàfi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, ẹ̀san tí kò níí pin ń bẹ fún wọn.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: