الفجر

تفسير سورة الفجر

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالْفَجْرِ﴾

Allāhu búra pẹ̀lú àfẹ̀mọ́júmọ́.

﴿وَلَيَالٍ عَشْرٍ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn òru mẹ́wàá kan.

﴿وَالشَّفْعِ وَالْوَتْرِ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú méjì àti ẹyọ.

﴿وَاللَّيْلِ إِذَا يَسْرِ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú òru nígbà tí ó bá lọ (tí ó bá dé).

﴿هَلْ فِي ذَٰلِكَ قَسَمٌ لِذِي حِجْرٍ﴾

Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?

﴿أَلَمْ تَرَ كَيْفَ فَعَلَ رَبُّكَ بِعَادٍ﴾

Ṣé o ò rí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,

﴿إِرَمَ ذَاتِ الْعِمَادِ﴾

(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,

﴿الَّتِي لَمْ يُخْلَقْ مِثْلُهَا فِي الْبِلَادِ﴾

àwọn tí A ò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?

﴿وَثَمُودَ الَّذِينَ جَابُوا الصَّخْرَ بِالْوَادِ﴾

Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonífojì,

﴿وَفِرْعَوْنَ ذِي الْأَوْتَادِ﴾

àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?

﴿الَّذِينَ طَغَوْا فِي الْبِلَادِ﴾

(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn t’ó tayọ ẹnu-àlà nínú ìlú.

﴿فَأَكْثَرُوا فِيهَا الْفَسَادَ﴾

Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.

﴿فَصَبَّ عَلَيْهِمْ رَبُّكَ سَوْطَ عَذَابٍ﴾

Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.

﴿إِنَّ رَبَّكَ لَبِالْمِرْصَادِ﴾

Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).

﴿فَأَمَّا الْإِنْسَانُ إِذَا مَا ابْتَلَاهُ رَبُّهُ فَأَكْرَمَهُ وَنَعَّمَهُ فَيَقُولُ رَبِّي أَكْرَمَنِ﴾

Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti pọ́n mi lé."

﴿وَأَمَّا إِذَا مَا ابْتَلَاهُ فَقَدَرَ عَلَيْهِ رِزْقَهُ فَيَقُولُ رَبِّي أَهَانَنِ﴾

Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi."

﴿كَلَّا ۖ بَلْ لَا تُكْرِمُونَ الْيَتِيمَ﴾

Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀. Àmọ́, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.

﴿وَلَا تَحَاضُّونَ عَلَىٰ طَعَامِ الْمِسْكِينِ﴾

Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.

﴿وَتَأْكُلُونَ التُّرَاثَ أَكْلًا لَمًّا﴾

Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.

﴿وَتُحِبُّونَ الْمَالَ حُبًّا جَمًّا﴾

Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.

﴿كَلَّا إِذَا دُكَّتِ الْأَرْضُ دَكًّا دَكًّا﴾

Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (t’ó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),

﴿وَجَاءَ رَبُّكَ وَالْمَلَكُ صَفًّا صَفًّا﴾

(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,

﴿وَجِيءَ يَوْمَئِذٍ بِجَهَنَّمَ ۚ يَوْمَئِذٍ يَتَذَكَّرُ الْإِنْسَانُ وَأَنَّىٰ لَهُ الذِّكْرَىٰ﴾

ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!

﴿يَقُولُ يَا لَيْتَنِي قَدَّمْتُ لِحَيَاتِي﴾

Ó máa wí pé: "Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi."

﴿فَيَوْمَئِذٍ لَا يُعَذِّبُ عَذَابَهُ أَحَدٌ﴾

Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).

﴿وَلَا يُوثِقُ وَثَاقَهُ أَحَدٌ﴾

Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).

﴿يَا أَيَّتُهَا النَّفْسُ الْمُطْمَئِنَّةُ﴾

Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,

﴿ارْجِعِي إِلَىٰ رَبِّكِ رَاضِيَةً مَرْضِيَّةً﴾

padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.

﴿فَادْخُلِي فِي عِبَادِي﴾

Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.

﴿وَادْخُلِي جَنَّتِي﴾

Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: