الشمس

تفسير سورة الشمس

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالشَّمْسِ وَضُحَاهَا﴾

(Allāhu) búra pẹ̀lú òòrùn àti ìyálẹ̀ta rẹ̀.

﴿وَالْقَمَرِ إِذَا تَلَاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú òṣùpá nígbà tí ó bá (yọ) tẹ̀lé (òòrùn).

﴿وَالنَّهَارِ إِذَا جَلَّاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí ó bá mú ìmọ́lẹ̀ bá òkùnkùn òru.

﴿وَاللَّيْلِ إِذَا يَغْشَاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá bo ọ̀sán mọ́lẹ̀.

﴿وَالسَّمَاءِ وَمَا بَنَاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú sánmọ̀ àti Ẹni tí Ó mọ ọ́n ?

﴿وَالْأَرْضِ وَمَا طَحَاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú ilẹ̀ àti Ẹni tí Ó tẹ́ ẹ kalẹ̀.

﴿وَنَفْسٍ وَمَا سَوَّاهَا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú ẹ̀mí (ènìyàn) àti Ẹni tí Ó ṣe (oríkèé rẹ̀) dọ́gba.

﴿فَأَلْهَمَهَا فُجُورَهَا وَتَقْوَاهَا﴾

Ó sì fi ẹ̀ṣẹ̀ (tí ẹ̀mí lè dá) àti ìbẹ̀rù rẹ̀ mọ̀ ọ́n.

﴿قَدْ أَفْلَحَ مَنْ زَكَّاهَا﴾

Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣàfọ̀mọ́ (ẹ̀mí ara) rẹ̀ (níbi ẹ̀ṣẹ̀), ó mà ti jèrè.

﴿وَقَدْ خَابَ مَنْ دَسَّاهَا﴾

Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi (ìwà ẹ̀ṣẹ̀) ba ẹ̀mí (ara) rẹ̀ jẹ́, ó mà ti pàdánù.

﴿كَذَّبَتْ ثَمُودُ بِطَغْوَاهَا﴾

Ìjọ Thamūd pe òdodo nírọ́ nípa ìtayọ ẹnu-àlà wọn.

﴿إِذِ انْبَعَثَ أَشْقَاهَا﴾

(Rántí) nígbà tí ẹni tí orí rẹ̀ burú jùlọ nínú wọn sáré dìde (láti gún ràkúnmí pa).

﴿فَقَالَ لَهُمْ رَسُولُ اللَّهِ نَاقَةَ اللَّهِ وَسُقْيَاهَا﴾

Nígbà náà, Òjíṣẹ́ Allāhu sọ fún wọn pé: "(Ẹ fi) abo ràkúnmí Allāhu àti omi rẹ̀ (sílẹ̀)."

﴿فَكَذَّبُوهُ فَعَقَرُوهَا فَدَمْدَمَ عَلَيْهِمْ رَبُّهُمْ بِذَنْبِهِمْ فَسَوَّاهَا﴾

Wọ́n pè é nírọ́. Wọ́n sì gún (ràkúnmí) pa. Nítorí náà, Olúwa wọn pa wọ́n rẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ó sì fi ìparun náà kárí wọn.

﴿وَلَا يَخَافُ عُقْبَاهَا﴾

(Ẹni t’ó gún ràkúnmí pa) kò sì páyà ìkángun ọ̀rọ̀ wọn.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: