النازعات

تفسير سورة النازعات

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالنَّازِعَاتِ غَرْقًا﴾

Allāhu búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́.

﴿وَالنَّاشِطَاتِ نَشْطًا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَالسَّابِحَاتِ سَبْحًا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀.

﴿فَالسَّابِقَاتِ سَبْقًا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà.

﴿فَالْمُدَبِّرَاتِ أَمْرًا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń ṣètò ilé ayé.

﴿يَوْمَ تَرْجُفُ الرَّاجِفَةُ﴾

Ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa mi gbogbo ayé tìtì pẹ̀lú ohùn igbe.

﴿تَتْبَعُهَا الرَّادِفَةُ﴾

Ìfọn kejì fún Àjíǹde sì máa tèlé e.

﴿قُلُوبٌ يَوْمَئِذٍ وَاجِفَةٌ﴾

Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.

﴿أَبْصَارُهَا خَاشِعَةٌ﴾

Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.

﴿يَقُولُونَ أَإِنَّا لَمَرْدُودُونَ فِي الْحَافِرَةِ﴾

Wọn yóò wí pé: "Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?

﴿أَإِذَا كُنَّا عِظَامًا نَخِرَةً﴾

Ṣé nígbà tí a ti di eegun t’ó kẹfun tán?"

﴿قَالُوا تِلْكَ إِذًا كَرَّةٌ خَاسِرَةٌ﴾

Wọ́n wí pé: "Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni t’ó pè é nírọ́.)"

﴿فَإِنَّمَا هِيَ زَجْرَةٌ وَاحِدَةٌ﴾

Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.

﴿فَإِذَا هُمْ بِالسَّاهِرَةِ﴾

Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.

﴿هَلْ أَتَاكَ حَدِيثُ مُوسَىٰ﴾

Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

﴿إِذْ نَادَاهُ رَبُّهُ بِالْوَادِ الْمُقَدَّسِ طُوًى﴾

(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonífojì mímọ́, Tuwā.

﴿اذْهَبْ إِلَىٰ فِرْعَوْنَ إِنَّهُ طَغَىٰ﴾

Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-àlà.

﴿فَقُلْ هَلْ لَكَ إِلَىٰ أَنْ تَزَكَّىٰ﴾

Kí o sì sọ pé: "Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?

﴿وَأَهْدِيَكَ إِلَىٰ رَبِّكَ فَتَخْشَىٰ﴾

Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, kí o páyà (Rẹ̀)."

﴿فَأَرَاهُ الْآيَةَ الْكُبْرَىٰ﴾

Ó sì fi àmì t’ó tóbi hàn án.

﴿فَكَذَّبَ وَعَصَىٰ﴾

(Àmọ́) ó pè é lópùrọ́. Ó sì yapa rẹ̀.

﴿ثُمَّ أَدْبَرَ يَسْعَىٰ﴾

Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).

﴿فَحَشَرَ فَنَادَىٰ﴾

Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.

﴿فَقَالَ أَنَا رَبُّكُمُ الْأَعْلَىٰ﴾

Ó sì wí pé: "Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ."

﴿فَأَخَذَهُ اللَّهُ نَكَالَ الْآخِرَةِ وَالْأُولَىٰ﴾

Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).

﴿إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَعِبْرَةً لِمَنْ يَخْشَىٰ﴾

Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni t’ó ń páyà (Allāhu).

﴿أَأَنْتُمْ أَشَدُّ خَلْقًا أَمِ السَّمَاءُ ۚ بَنَاهَا﴾

Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?

﴿رَفَعَ سَمْكَهَا فَسَوَّاهَا﴾

Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé t’ó gún régé.

﴿وَأَغْطَشَ لَيْلَهَا وَأَخْرَجَ ضُحَاهَا﴾

Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.

﴿وَالْأَرْضَ بَعْدَ ذَٰلِكَ دَحَاهَا﴾

Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.

﴿أَخْرَجَ مِنْهَا مَاءَهَا وَمَرْعَاهَا﴾

Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.

﴿وَالْجِبَالَ أَرْسَاهَا﴾

Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.

﴿مَتَاعًا لَكُمْ وَلِأَنْعَامِكُمْ﴾

Ìgbádùn ni fun yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.

﴿فَإِذَا جَاءَتِ الطَّامَّةُ الْكُبْرَىٰ﴾

Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,

﴿يَوْمَ يَتَذَكَّرُ الْإِنْسَانُ مَا سَعَىٰ﴾

ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun t’ó ṣe níṣẹ́.

﴿وَبُرِّزَتِ الْجَحِيمُ لِمَنْ يَرَىٰ﴾

Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni t’ó ríran.

﴿فَأَمَّا مَنْ طَغَىٰ﴾

Nítorí náà, ní ti ẹni t’ó bá tayọ ẹnu-àlà,

﴿وَآثَرَ الْحَيَاةَ الدُّنْيَا﴾

tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,

﴿فَإِنَّ الْجَحِيمَ هِيَ الْمَأْوَىٰ﴾

dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

﴿وَأَمَّا مَنْ خَافَ مَقَامَ رَبِّهِ وَنَهَى النَّفْسَ عَنِ الْهَوَىٰ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),

﴿فَإِنَّ الْجَنَّةَ هِيَ الْمَأْوَىٰ﴾

dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).

﴿يَسْأَلُونَكَ عَنِ السَّاعَةِ أَيَّانَ مُرْسَاهَا﴾

Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: "Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?"

﴿فِيمَ أَنْتَ مِنْ ذِكْرَاهَا﴾

Ọ̀nà wo ni ìwọ lè fi ní (ìmọ̀) ìrántí rẹ̀ ná?

﴿إِلَىٰ رَبِّكَ مُنْتَهَاهَا﴾

Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.

﴿إِنَّمَا أَنْتَ مُنْذِرُ مَنْ يَخْشَاهَا﴾

Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni t’ó ń páyà rẹ̀.

﴿كَأَنَّهُمْ يَوْمَ يَرَوْنَهَا لَمْ يَلْبَثُوا إِلَّا عَشِيَّةً أَوْ ضُحَاهَا﴾

Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò lò tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan lọ (nílé ayé).

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: