الواقعة

تفسير سورة الواقعة

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ إِذَا وَقَعَتِ الْوَاقِعَةُ﴾

Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,

﴿لَيْسَ لِوَقْعَتِهَا كَاذِبَةٌ﴾

- kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-E4983

﴿خَافِضَةٌ رَافِعَةٌ﴾

ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).

﴿إِذَا رُجَّتِ الْأَرْضُ رَجًّا﴾

Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,

﴿وَبُسَّتِ الْجِبَالُ بَسًّا﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,

﴿فَكَانَتْ هَبَاءً مُنْبَثًّا﴾

- wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù - E4987

﴿وَكُنْتُمْ أَزْوَاجًا ثَلَاثَةً﴾

ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.

﴿فَأَصْحَابُ الْمَيْمَنَةِ مَا أَصْحَابُ الْمَيْمَنَةِ﴾

Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?

﴿وَأَصْحَابُ الْمَشْأَمَةِ مَا أَصْحَابُ الْمَشْأَمَةِ﴾

Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?

﴿وَالسَّابِقُونَ السَّابِقُونَ﴾

Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.

﴿أُولَٰئِكَ الْمُقَرَّبُونَ﴾

Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)

﴿فِي جَنَّاتِ النَّعِيمِ﴾

nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.

﴿ثُلَّةٌ مِنَ الْأَوَّلِينَ﴾

Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.

﴿وَقَلِيلٌ مِنَ الْآخِرِينَ﴾

Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.

﴿عَلَىٰ سُرُرٍ مَوْضُونَةٍ﴾

(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.

﴿مُتَّكِئِينَ عَلَيْهَا مُتَقَابِلِينَ﴾

Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.

﴿يَطُوفُ عَلَيْهِمْ وِلْدَانٌ مُخَلَّدُونَ﴾

Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn

﴿بِأَكْوَابٍ وَأَبَارِيقَ وَكَأْسٍ مِنْ مَعِينٍ﴾

pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn.

﴿لَا يُصَدَّعُونَ عَنْهَا وَلَا يُنْزِفُونَ﴾

Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.

﴿وَفَاكِهَةٍ مِمَّا يَتَخَيَّرُونَ﴾

Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).

﴿وَلَحْمِ طَيْرٍ مِمَّا يَشْتَهُونَ﴾

Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).

﴿وَحُورٌ عِينٌ﴾

Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).

﴿كَأَمْثَالِ اللُّؤْلُؤِ الْمَكْنُونِ﴾

Wọ́n dà bí òkúta olówó-iyebíye tí wọ́n fi pamọ́.

﴿جَزَاءً بِمَا كَانُوا يَعْمَلُونَ﴾

(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.

﴿لَا يَسْمَعُونَ فِيهَا لَغْوًا وَلَا تَأْثِيمًا﴾

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.

﴿إِلَّا قِيلًا سَلَامًا سَلَامًا﴾

Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.

﴿وَأَصْحَابُ الْيَمِينِ مَا أَصْحَابُ الْيَمِينِ﴾

Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?

﴿فِي سِدْرٍ مَخْضُودٍ﴾

(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,

﴿وَطَلْحٍ مَنْضُودٍ﴾

àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ t’ó so jìgbìnnì,

﴿وَظِلٍّ مَمْدُودٍ﴾

àti ibòji t’ó gbòòrò,

﴿وَمَاءٍ مَسْكُوبٍ﴾

àti omi t’ó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,

﴿وَفَاكِهَةٍ كَثِيرَةٍ﴾

àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,

﴿لَا مَقْطُوعَةٍ وَلَا مَمْنُوعَةٍ﴾

tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).

﴿وَفُرُشٍ مَرْفُوعَةٍ﴾

(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.

﴿إِنَّا أَنْشَأْنَاهُنَّ إِنْشَاءً﴾

Dájúdájú Àwa tún (àwọn obìnrin wọn) dá ní ẹ̀dá ọ̀tun.

﴿فَجَعَلْنَاهُنَّ أَبْكَارًا﴾

A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,

﴿عُرُبًا أَتْرَابًا﴾

olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.

﴿لِأَصْحَابِ الْيَمِينِ﴾

(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.

﴿ثُلَّةٌ مِنَ الْأَوَّلِينَ﴾

Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.

﴿وَثُلَّةٌ مِنَ الْآخِرِينَ﴾

Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.

﴿وَأَصْحَابُ الشِّمَالِ مَا أَصْحَابُ الشِّمَالِ﴾

Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?

﴿فِي سَمُومٍ وَحَمِيمٍ﴾

(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná àti omi gbígbóná,

﴿وَظِلٍّ مِنْ يَحْمُومٍ﴾

àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,

﴿لَا بَارِدٍ وَلَا كَرِيمٍ﴾

kò tutù, kò sì dára.

﴿إِنَّهُمْ كَانُوا قَبْلَ ذَٰلِكَ مُتْرَفِينَ﴾

Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.

﴿وَكَانُوا يُصِرُّونَ عَلَى الْحِنْثِ الْعَظِيمِ﴾

Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

﴿وَكَانُوا يَقُولُونَ أَئِذَا مِتْنَا وَكُنَّا تُرَابًا وَعِظَامًا أَإِنَّا لَمَبْعُوثُونَ﴾

Wọ́n sì máa ń wí pé: "Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?

﴿أَوَآبَاؤُنَا الْأَوَّلُونَ﴾

Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"

﴿قُلْ إِنَّ الْأَوَّلِينَ وَالْآخِرِينَ﴾

Sọ pé: "Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,

﴿لَمَجْمُوعُونَ إِلَىٰ مِيقَاتِ يَوْمٍ مَعْلُومٍ﴾

dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀."

﴿ثُمَّ إِنَّكُمْ أَيُّهَا الضَّالُّونَ الْمُكَذِّبُونَ﴾

Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,

﴿لَآكِلُونَ مِنْ شَجَرٍ مِنْ زَقُّومٍ﴾

dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).

﴿فَمَالِئُونَ مِنْهَا الْبُطُونَ﴾

Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.

﴿فَشَارِبُونَ عَلَيْهِ مِنَ الْحَمِيمِ﴾

Ẹ̀yin yó sì máa mu omi gbígbóná lé e lórí.

﴿فَشَارِبُونَ شُرْبَ الْهِيمِ﴾

Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.

﴿هَٰذَا نُزُلُهُمْ يَوْمَ الدِّينِ﴾

Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.

﴿نَحْنُ خَلَقْنَاكُمْ فَلَوْلَا تُصَدِّقُونَ﴾

Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ lódodo!

﴿أَفَرَأَيْتُمْ مَا تُمْنُونَ﴾

Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),

﴿أَأَنْتُمْ تَخْلُقُونَهُ أَمْ نَحْنُ الْخَالِقُونَ﴾

ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?

﴿نَحْنُ قَدَّرْنَا بَيْنَكُمُ الْمَوْتَ وَمَا نَحْنُ بِمَسْبُوقِينَ﴾

Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Àwa kò sì lè kágara

﴿عَلَىٰ أَنْ نُبَدِّلَ أَمْثَالَكُمْ وَنُنْشِئَكُمْ فِي مَا لَا تَعْلَمُونَ﴾

láti fi irú yín pààrọ̀ yín, kí á sì tun yín dá sínú ohun tí ẹ kò mọ̀.

﴿وَلَقَدْ عَلِمْتُمُ النَّشْأَةَ الْأُولَىٰ فَلَوْلَا تَذَكَّرُونَ﴾

Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́, ẹ ò ṣe lo ìrántí?

﴿أَفَرَأَيْتُمْ مَا تَحْرُثُونَ﴾

Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,

﴿أَأَنْتُمْ تَزْرَعُونَهُ أَمْ نَحْنُ الزَّارِعُونَ﴾

ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde ni tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?

﴿لَوْ نَشَاءُ لَجَعَلْنَاهُ حُطَامًا فَظَلْتُمْ تَفَكَّهُونَ﴾

Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).

﴿إِنَّا لَمُغْرَمُونَ﴾

(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) "Dájúdájú àwa ti di onígbèsè."

﴿بَلْ نَحْنُ مَحْرُومُونَ﴾

(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) "Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni."

﴿أَفَرَأَيْتُمُ الْمَاءَ الَّذِي تَشْرَبُونَ﴾

Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,

﴿أَأَنْتُمْ أَنْزَلْتُمُوهُ مِنَ الْمُزْنِ أَمْ نَحْنُ الْمُنْزِلُونَ﴾

ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?

﴿لَوْ نَشَاءُ جَعَلْنَاهُ أُجَاجًا فَلَوْلَا تَشْكُرُونَ﴾

Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi t’ó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?

﴿أَفَرَأَيْتُمُ النَّارَ الَّتِي تُورُونَ﴾

Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,

﴿أَأَنْتُمْ أَنْشَأْتُمْ شَجَرَتَهَا أَمْ نَحْنُ الْمُنْشِئُونَ﴾

ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?

﴿نَحْنُ جَعَلْنَاهَا تَذْكِرَةً وَمَتَاعًا لِلْمُقْوِينَ﴾

Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.

﴿فَسَبِّحْ بِاسْمِ رَبِّكَ الْعَظِيمِ﴾

Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.

﴿۞ فَلَا أُقْسِمُ بِمَوَاقِعِ النُّجُومِ﴾

Mò ń búra pẹ̀lú àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀.

﴿وَإِنَّهُ لَقَسَمٌ لَوْ تَعْلَمُونَ عَظِيمٌ﴾

Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.

﴿إِنَّهُ لَقُرْآنٌ كَرِيمٌ﴾

Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé,

﴿فِي كِتَابٍ مَكْنُونٍ﴾

(t’ó wà) nínú Tírà ààbò (nínú Laohul-Mahfūṭḥ).

﴿لَا يَمَسُّهُ إِلَّا الْمُطَهَّرُونَ﴾

Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).

﴿تَنْزِيلٌ مِنْ رَبِّ الْعَالَمِينَ﴾

Wọ́n sọ̀ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

﴿أَفَبِهَٰذَا الْحَدِيثِ أَنْتُمْ مُدْهِنُونَ﴾

Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè nírọ́?

﴿وَتَجْعَلُونَ رِزْقَكُمْ أَنَّكُمْ تُكَذِّبُونَ﴾

Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo nírọ́.

﴿فَلَوْلَا إِذَا بَلَغَتِ الْحُلْقُومَ﴾

Kí ni ó máa ti rí (fun yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,

﴿وَأَنْتُمْ حِينَئِذٍ تَنْظُرُونَ﴾

tí ẹ̀yin yó sì máa wòran nígbà yẹn?

﴿وَنَحْنُ أَقْرَبُ إِلَيْهِ مِنْكُمْ وَلَٰكِنْ لَا تُبْصِرُونَ﴾

Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.

﴿فَلَوْلَا إِنْ كُنْتُمْ غَيْرَ مَدِينِينَ﴾

Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,

﴿تَرْجِعُونَهَا إِنْ كُنْتُمْ صَادِقِينَ﴾

kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.

﴿فَأَمَّا إِنْ كَانَ مِنَ الْمُقَرَّبِينَ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),

﴿فَرَوْحٌ وَرَيْحَانٌ وَجَنَّتُ نَعِيمٍ﴾

ìsinmi, èsè t’ó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).

﴿وَأَمَّا إِنْ كَانَ مِنْ أَصْحَابِ الْيَمِينِ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,

﴿فَسَلَامٌ لَكَ مِنْ أَصْحَابِ الْيَمِينِ﴾

àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.

﴿وَأَمَّا إِنْ كَانَ مِنَ الْمُكَذِّبِينَ الضَّالِّينَ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,

﴿فَنُزُلٌ مِنْ حَمِيمٍ﴾

n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi gbígbóná

﴿وَتَصْلِيَةُ جَحِيمٍ﴾

àti wíwọ inú iná Jẹhīm.

﴿إِنَّ هَٰذَا لَهُوَ حَقُّ الْيَقِينِ﴾

Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo t’ó dájú.

﴿فَسَبِّحْ بِاسْمِ رَبِّكَ الْعَظِيمِ﴾

Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: