التكوير

تفسير سورة التكوير

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ إِذَا الشَّمْسُ كُوِّرَتْ﴾

Nígbà tí Wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,

﴿وَإِذَا النُّجُومُ انْكَدَرَتْ﴾

àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,

﴿وَإِذَا الْجِبَالُ سُيِّرَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),

﴿وَإِذَا الْعِشَارُ عُطِّلَتْ﴾

àti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,

﴿وَإِذَا الْوُحُوشُ حُشِرَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,

﴿وَإِذَا الْبِحَارُ سُجِّرَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,

﴿وَإِذَا النُّفُوسُ زُوِّجَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)

﴿وَإِذَا الْمَوْءُودَةُ سُئِلَتْ﴾

àti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé

﴿بِأَيِّ ذَنْبٍ قُتِلَتْ﴾

ẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,

﴿وَإِذَا الصُّحُفُ نُشِرَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,

﴿وَإِذَا السَّمَاءُ كُشِطَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,

﴿وَإِذَا الْجَحِيمُ سُعِّرَتْ﴾

àti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,

﴿وَإِذَا الْجَنَّةُ أُزْلِفَتْ﴾

àti nígbà tí Wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),

﴿عَلِمَتْ نَفْسٌ مَا أَحْضَرَتْ﴾

(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).

﴿فَلَا أُقْسِمُ بِالْخُنَّسِ﴾

Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwọn ìràwọ̀ t’ó ń yọ ní alẹ́, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán,

﴿الْجَوَارِ الْكُنَّسِ﴾

(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ t’ó ń rìn lọ rìn bọ̀, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.

﴿وَاللَّيْلِ إِذَا عَسْعَسَ﴾

Mo tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.

﴿وَالصُّبْحِ إِذَا تَنَفَّسَ﴾

Mo tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀.

﴿إِنَّهُ لَقَوْلُ رَسُولٍ كَرِيمٍ﴾

Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,

﴿ذِي قُوَّةٍ عِنْدَ ذِي الْعَرْشِ مَكِينٍ﴾

alágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,

﴿مُطَاعٍ ثَمَّ أَمِينٍ﴾

ẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.

﴿وَمَا صَاحِبُكُمْ بِمَجْنُونٍ﴾

Àti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad s.a.w.) kì í ṣe wèrè.

﴿وَلَقَدْ رَآهُ بِالْأُفُقِ الْمُبِينِ﴾

Ó kúkú rí i nínú òfurufú kedere.

﴿وَمَا هُوَ عَلَى الْغَيْبِ بِضَنِينٍ﴾

Àti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).

﴿وَمَا هُوَ بِقَوْلِ شَيْطَانٍ رَجِيمٍ﴾

Al-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Èṣù, ẹni ẹ̀kọ̀.

﴿فَأَيْنَ تَذْهَبُونَ﴾

Nítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?

﴿إِنْ هُوَ إِلَّا ذِكْرٌ لِلْعَالَمِينَ﴾

Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.

﴿لِمَنْ شَاءَ مِنْكُمْ أَنْ يَسْتَقِيمَ﴾

(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.

﴿وَمَا تَشَاءُونَ إِلَّا أَنْ يَشَاءَ اللَّهُ رَبُّ الْعَالَمِينَ﴾

Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: