الليل

تفسير سورة الليل

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَاللَّيْلِ إِذَا يَغْشَىٰ﴾

(Allāhu) búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú.

﴿وَالنَّهَارِ إِذَا تَجَلَّىٰ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n.

﴿وَمَا خَلَقَ الذَّكَرَ وَالْأُنْثَىٰ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú Ẹni tí Ó dá akọ àti abo.

﴿إِنَّ سَعْيَكُمْ لَشَتَّىٰ﴾

Dájúdájú iṣẹ́ yín, ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni.

﴿فَأَمَّا مَنْ أَعْطَىٰ وَاتَّقَىٰ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),

﴿وَصَدَّقَ بِالْحُسْنَىٰ﴾

(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní òdodo,

﴿فَسَنُيَسِّرُهُ لِلْيُسْرَىٰ﴾

A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.

﴿وَأَمَّا مَنْ بَخِلَ وَاسْتَغْنَىٰ﴾

Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni t’ó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,

﴿وَكَذَّبَ بِالْحُسْنَىٰ﴾

(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní irọ́,

﴿فَسَنُيَسِّرُهُ لِلْعُسْرَىٰ﴾

A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.

﴿وَمَا يُغْنِي عَنْهُ مَالُهُ إِذَا تَرَدَّىٰ﴾

Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá já bọ́ (sínú Iná).

﴿إِنَّ عَلَيْنَا لَلْهُدَىٰ﴾

Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.

﴿وَإِنَّ لَنَا لَلْآخِرَةَ وَالْأُولَىٰ﴾

Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.

﴿فَأَنْذَرْتُكُمْ نَارًا تَلَظَّىٰ﴾

Nítorí náà, Mo ti fi Iná eléjò fòfò kìlọ̀ fun yín.

﴿لَا يَصْلَاهَا إِلَّا الْأَشْقَى﴾

Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,

﴿الَّذِي كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ﴾

ẹni tí ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.

﴿وَسَيُجَنَّبُهَا الْأَتْقَى﴾

Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),

﴿الَّذِي يُؤْتِي مَالَهُ يَتَزَكَّىٰ﴾

ẹni t’ó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).

﴿وَمَا لِأَحَدٍ عِنْدَهُ مِنْ نِعْمَةٍ تُجْزَىٰ﴾

Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,

﴿إِلَّا ابْتِغَاءَ وَجْهِ رَبِّهِ الْأَعْلَىٰ﴾

bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.

﴿وَلَسَوْفَ يَرْضَىٰ﴾

Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rẹ̀).

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: