البروج

تفسير سورة البروج

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالسَّمَاءِ ذَاتِ الْبُرُوجِ﴾

(Allāhu) búra pẹ̀lú sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀.

﴿وَالْيَوْمِ الْمَوْعُودِ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn.

﴿وَشَاهِدٍ وَمَشْهُودٍ﴾

Ó tún búra pẹ̀lú olùjẹ́rìí àti ohun t’ó jẹ́rìí sí.

﴿قُتِلَ أَصْحَابُ الْأُخْدُودِ﴾

A ṣẹ́bi lé àwọn t’ó gbẹ́ kòtò (iná),

﴿النَّارِ ذَاتِ الْوَقُودِ﴾

. (ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).

﴿إِذْ هُمْ عَلَيْهَا قُعُودٌ﴾

(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.

﴿وَهُمْ عَلَىٰ مَا يَفْعَلُونَ بِالْمُؤْمِنِينَ شُهُودٌ﴾

Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.

﴿وَمَا نَقَمُوا مِنْهُمْ إِلَّا أَنْ يُؤْمِنُوا بِاللَّهِ الْعَزِيزِ الْحَمِيدِ﴾

Kò sì sí kiní kan tí wọ́n torí rẹ̀ jẹ wọ́n níyà bí kò ṣe pé wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ọlọ́pẹ́,

﴿الَّذِي لَهُ مُلْكُ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ ۚ وَاللَّهُ عَلَىٰ كُلِّ شَيْءٍ شَهِيدٌ﴾

Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.

﴿إِنَّ الَّذِينَ فَتَنُوا الْمُؤْمِنِينَ وَالْمُؤْمِنَاتِ ثُمَّ لَمْ يَتُوبُوا فَلَهُمْ عَذَابُ جَهَنَّمَ وَلَهُمْ عَذَابُ الْحَرِيقِ﴾

Dájúdájú àwọn t’ó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná t’ó ń jò sì wà fún wọn.

﴿إِنَّ الَّذِينَ آمَنُوا وَعَمِلُوا الصَّالِحَاتِ لَهُمْ جَنَّاتٌ تَجْرِي مِنْ تَحْتِهَا الْأَنْهَارُ ۚ ذَٰلِكَ الْفَوْزُ الْكَبِيرُ﴾

Dájúdájú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.

﴿إِنَّ بَطْشَ رَبِّكَ لَشَدِيدٌ﴾

Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.

﴿إِنَّهُ هُوَ يُبْدِئُ وَيُعِيدُ﴾

Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).

﴿وَهُوَ الْغَفُورُ الْوَدُودُ﴾

Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),

﴿ذُو الْعَرْشِ الْمَجِيدُ﴾

Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ,

﴿فَعَّالٌ لِمَا يُرِيدُ﴾

Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.

﴿هَلْ أَتَاكَ حَدِيثُ الْجُنُودِ﴾

Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,

﴿فِرْعَوْنَ وَثَمُودَ﴾

(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?

﴿بَلِ الَّذِينَ كَفَرُوا فِي تَكْذِيبٍ﴾

Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo nírọ́.

﴿وَاللَّهُ مِنْ وَرَائِهِمْ مُحِيطٌ﴾

Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.

﴿بَلْ هُوَ قُرْآنٌ مَجِيدٌ﴾

Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,

﴿فِي لَوْحٍ مَحْفُوظٍ﴾

tí ó wà nínú wàláà tí À ń ṣọ́.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: