الغاشية

تفسير سورة الغاشية

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ هَلْ أَتَاكَ حَدِيثُ الْغَاشِيَةِ﴾

Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ nípa ohun t’ó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?

﴿وُجُوهٌ يَوْمَئِذٍ خَاشِعَةٌ﴾

Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.

﴿عَامِلَةٌ نَاصِبَةٌ﴾

Oníṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni wọ́n nílé ayé).

﴿تَصْلَىٰ نَارًا حَامِيَةً﴾

Wọ́n máa wọ inú Iná t’ó gbóná janjan (ní ọ̀run).

﴿تُسْقَىٰ مِنْ عَيْنٍ آنِيَةٍ﴾

Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi gbígbóná mu.

﴿لَيْسَ لَهُمْ طَعَامٌ إِلَّا مِنْ ضَرِيعٍ﴾

Kò sí oúnjẹ kan fún wọn àyàfi igi ẹlẹ́gùn-ún gbígbẹ.

﴿لَا يُسْمِنُ وَلَا يُغْنِي مِنْ جُوعٍ﴾

Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.

﴿وُجُوهٌ يَوْمَئِذٍ نَاعِمَةٌ﴾

Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn

﴿لِسَعْيِهَا رَاضِيَةٌ﴾

nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.

﴿فِي جَنَّةٍ عَالِيَةٍ﴾

(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.

﴿لَا تَسْمَعُ فِيهَا لَاغِيَةً﴾

Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.

﴿فِيهَا عَيْنٌ جَارِيَةٌ﴾

Omi ìṣẹ́lẹ̀rú t’ó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.

﴿فِيهَا سُرُرٌ مَرْفُوعَةٌ﴾

Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,

﴿وَأَكْوَابٌ مَوْضُوعَةٌ﴾

àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),

﴿وَنَمَارِقُ مَصْفُوفَةٌ﴾

àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,

﴿وَزَرَابِيُّ مَبْثُوثَةٌ﴾

àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.

﴿أَفَلَا يَنْظُرُونَ إِلَى الْإِبِلِ كَيْفَ خُلِقَتْ﴾

Nítorí náà, ṣé wọn kò wo ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;

﴿وَإِلَى السَّمَاءِ كَيْفَ رُفِعَتْ﴾

àti sánmọ̀, bí A ti ṣe gbé e sókè;

﴿وَإِلَى الْجِبَالِ كَيْفَ نُصِبَتْ﴾

àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);

﴿وَإِلَى الْأَرْضِ كَيْفَ سُطِحَتْ﴾

àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ ní gban̄sasa?

﴿فَذَكِّرْ إِنَّمَا أَنْتَ مُذَكِّرٌ﴾

Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.

﴿لَسْتَ عَلَيْهِمْ بِمُصَيْطِرٍ﴾

Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn

﴿إِلَّا مَنْ تَوَلَّىٰ وَكَفَرَ﴾

àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.

﴿فَيُعَذِّبُهُ اللَّهُ الْعَذَابَ الْأَكْبَرَ﴾

Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà t’ó tóbi jùlọ.

﴿إِنَّ إِلَيْنَا إِيَابَهُمْ﴾

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.

﴿ثُمَّ إِنَّ عَلَيْنَا حِسَابَهُمْ﴾

Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: