العلق

تفسير سورة العلق

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ اقْرَأْ بِاسْمِ رَبِّكَ الَّذِي خَلَقَ﴾

Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.

﴿خَلَقَ الْإِنْسَانَ مِنْ عَلَقٍ﴾

Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.

﴿اقْرَأْ وَرَبُّكَ الْأَكْرَمُ﴾

Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.

﴿الَّذِي عَلَّمَ بِالْقَلَمِ﴾

Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.

﴿عَلَّمَ الْإِنْسَانَ مَا لَمْ يَعْلَمْ﴾

Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.

﴿كَلَّا إِنَّ الْإِنْسَانَ لَيَطْغَىٰ﴾

Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-àlà

﴿أَنْ رَآهُ اسْتَغْنَىٰ﴾

nítorí pé ó ríra rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.

﴿إِنَّ إِلَىٰ رَبِّكَ الرُّجْعَىٰ﴾

Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.

﴿أَرَأَيْتَ الَّذِي يَنْهَىٰ﴾

Sọ fún mi nípa ẹni t’ó ń kọ̀

﴿عَبْدًا إِذَا صَلَّىٰ﴾

fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!

﴿أَرَأَيْتَ إِنْ كَانَ عَلَى الْهُدَىٰ﴾

Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)

﴿أَوْ أَمَرَ بِالتَّقْوَىٰ﴾

tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!

﴿أَرَأَيْتَ إِنْ كَذَّبَ وَتَوَلَّىٰ﴾

Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?

﴿أَلَمْ يَعْلَمْ بِأَنَّ اللَّهَ يَرَىٰ﴾

Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)

﴿كَلَّا لَئِنْ لَمْ يَنْتَهِ لَنَسْفَعًا بِالنَّاصِيَةِ﴾

Bẹ́ẹ̀ ni (Allāhu ń rí i.) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí i lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);

﴿نَاصِيَةٍ كَاذِبَةٍ خَاطِئَةٍ﴾

àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.

﴿فَلْيَدْعُ نَادِيَهُ﴾

Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.

﴿سَنَدْعُ الزَّبَانِيَةَ﴾

Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.

﴿كَلَّا لَا تُطِعْهُ وَاسْجُدْ وَاقْتَرِبْ ۩﴾

Rárá o, má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o súnmọ́ (Allāhu).

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: