المرسلات

تفسير سورة المرسلات

الترجمة اليورباوية

Yorùbá

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني القرآن الكريم للغة اليوربا ترجمها الشيخ أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني عام الطبعة 1432هـ .

﴿بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ وَالْمُرْسَلَاتِ عُرْفًا﴾

Allāhu búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé.

﴿فَالْعَاصِفَاتِ عَصْفًا﴾

Ó búra pẹ̀lú àwọn ìjì atẹ́gùn t’ó ń jà.

﴿وَالنَّاشِرَاتِ نَشْرًا﴾

Ó búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń tú èṣújò ká.

﴿فَالْفَارِقَاتِ فَرْقًا﴾

Ó búra pẹ̀lú àwọn t’ó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́.

﴿فَالْمُلْقِيَاتِ ذِكْرًا﴾

Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́).

﴿عُذْرًا أَوْ نُذْرًا﴾

(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.

﴿إِنَّمَا تُوعَدُونَ لَوَاقِعٌ﴾

Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fun yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.

﴿فَإِذَا النُّجُومُ طُمِسَتْ﴾

Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,

﴿وَإِذَا السَّمَاءُ فُرِجَتْ﴾

àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,

﴿وَإِذَا الْجِبَالُ نُسِفَتْ﴾

àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,

﴿وَإِذَا الرُّسُلُ أُقِّتَتْ﴾

àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ, (Àkókò náà ti dé nìyẹn).

﴿لِأَيِّ يَوْمٍ أُجِّلَتْ﴾

Ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?

﴿لِيَوْمِ الْفَصْلِ﴾

Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.

﴿وَمَا أَدْرَاكَ مَا يَوْمُ الْفَصْلِ﴾

Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿أَلَمْ نُهْلِكِ الْأَوَّلِينَ﴾

Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?

﴿ثُمَّ نُتْبِعُهُمُ الْآخِرِينَ﴾

Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).

﴿كَذَٰلِكَ نَفْعَلُ بِالْمُجْرِمِينَ﴾

Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿أَلَمْ نَخْلُقْكُمْ مِنْ مَاءٍ مَهِينٍ﴾

Ṣé A ò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?

﴿فَجَعَلْنَاهُ فِي قَرَارٍ مَكِينٍ﴾

Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)

﴿إِلَىٰ قَدَرٍ مَعْلُومٍ﴾

títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).

﴿فَقَدَرْنَا فَنِعْمَ الْقَادِرُونَ﴾

A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀). (Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá t’ó dára.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿أَلَمْ نَجْعَلِ الْأَرْضَ كِفَاتًا﴾

Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun t’ó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;

﴿أَحْيَاءً وَأَمْوَاتًا﴾

(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?

﴿وَجَعَلْنَا فِيهَا رَوَاسِيَ شَامِخَاتٍ وَأَسْقَيْنَاكُمْ مَاءً فُرَاتًا﴾

A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fun yín ní omi dídùn mu.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿انْطَلِقُوا إِلَىٰ مَا كُنْتُمْ بِهِ تُكَذِّبُونَ﴾

Ẹ máa lọ sí ibi tí ẹ̀ ń pè nírọ́.

﴿انْطَلِقُوا إِلَىٰ ظِلٍّ ذِي ثَلَاثِ شُعَبٍ﴾

Ẹ máa lọ sí ibi èéfín ẹlẹ́ka mẹ́ta.

﴿لَا ظَلِيلٍ وَلَا يُغْنِي مِنَ اللَّهَبِ﴾

Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.

﴿إِنَّهَا تَرْمِي بِشَرَرٍ كَالْقَصْرِ﴾

Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè t’ó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.

﴿كَأَنَّهُ جِمَالَتٌ صُفْرٌ﴾

(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿هَٰذَا يَوْمُ لَا يَنْطِقُونَ﴾

Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.

﴿وَلَا يُؤْذَنُ لَهُمْ فَيَعْتَذِرُونَ﴾

A ò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿هَٰذَا يَوْمُ الْفَصْلِ ۖ جَمَعْنَاكُمْ وَالْأَوَّلِينَ﴾

Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.

﴿فَإِنْ كَانَ لَكُمْ كَيْدٌ فَكِيدُونِ﴾

Tí ẹ bá ní ète kan lọ́wọ́, ẹ déte sí Mi wò.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿إِنَّ الْمُتَّقِينَ فِي ظِلَالٍ وَعُيُونٍ﴾

Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,

﴿وَفَوَاكِهَ مِمَّا يَشْتَهُونَ﴾

àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.

﴿كُلُوا وَاشْرَبُوا هَنِيئًا بِمَا كُنْتُمْ تَعْمَلُونَ﴾

Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.

﴿إِنَّا كَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ﴾

Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿كُلُوا وَتَمَتَّعُوا قَلِيلًا إِنَّكُمْ مُجْرِمُونَ﴾

Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿وَإِذَا قِيلَ لَهُمُ ارْكَعُوا لَا يَرْكَعُونَ﴾

Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.

﴿وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِلْمُكَذِّبِينَ﴾

Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.

﴿فَبِأَيِّ حَدِيثٍ بَعْدَهُ يُؤْمِنُونَ﴾

Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?

الترجمات والتفاسير لهذه السورة: